< Leviticus 18 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé:
OLELO mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé: ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
E olelo aku i na mamo a Iseraela, a e i aku ia lakou, Owau no Iehova ko oukou Akua.
3 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní Ejibiti níbi tí ẹ ti gbé rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní ilẹ̀ Kenaani níbi tí èmi ń mú yín lọ. Ẹ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ìṣe wọn.
Mamuli o na hana a ka aina o Aigupita, kahi i noho ai oukou, aole oukou e hana aku; a mamuli o na hana a ka aina o Kanaana, kahi e lawe ae ai au ia oukou, aole oukou e hana aku; aole hoi oukou e hele ma ka lakou mau oihana.
4 Kí ẹ̀yin kí ó sì máa ṣe òfin mi, kí ẹ̀yin sì máa pa ìlànà mi mọ́, láti máa rìn nínú wọn, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
E hana hoi oukou ma ko'u mau kanawai, a e malama i ka'u mau oihana, e hele malaila: owau no Iehova ko oukou Akua.
5 Ẹ̀yin ó sì máa pa ìlànà mi mọ́ àti òfin mi; Ẹni tí ó ba ṣe, yóò yè nípa wọn. Èmi ni Olúwa.
Nolaila, e malama oukou i ka'u mau kauoha, a me ko'u mau kanawai: ina e hana ke kanaka ia, e ola no oia ia mau mea: owau no Iehova.
6 “‘Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ súnmọ́ ìbátan rẹ̀ láti bá a lòpọ̀. Èmí ni Olúwa.
Aole kekahi o oukou e hookokoke aku i ka io o kona io iho; e wehe i kahi huna: owau no Iehova.
7 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyá rẹ lòpọ̀, ìyá rẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ bá a lòpọ̀.
O kahi huna o kou makuakane, a o kahi huna o kou makuwahine, mai wehe oe: o kou makuwahine no ia, mai wehe oe i kahi huna ona.
8 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyàwó baba rẹ lòpọ̀, nítorí ìhòhò baba rẹ ni.
O kahi huna o ka wahine a kou makuakane, mai wehe oe: o kahi huna ia o kou makuakane.
9 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin rẹ tí ó jẹ́ ọmọ ìyá rẹ lòpọ̀, yálà a bí i nílé yín tàbí lóde.
O kahi huna o kou kaikuwahine, o ke kaikamahine a kou makuakane, o ke kaikamahine o kou makuwahine paha, ua hanau ma kou wahi noho paha, ua hanau ma kahi e paha, mai wehe oe i kahi huna o laua.
10 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin, ọmọ rẹ ọkùnrin lòpọ̀ tàbí ọmọbìnrin ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀ nítorí pé ìhòhò wọn, ìhòhò ìwọ fúnra rẹ̀ ni.
O kahi huna o ke kaikamahine a kau keikikane, a me ke kaikamahine a kau kaikamahine, mai wehe oe i kahi huna o laua: no ka mea, o ko laua, o kou wahi huna no ia.
11 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin aya baba rẹ lòpọ̀; èyí tí a bí fún baba rẹ nítorí pé arábìnrin rẹ ni.
O kahi huna o ke kaikamahine a ka wahine a kou makuakane, na kou makuakane i hanau, o kou kaikuwahine no ia, mai wehe oe i kona wahi huna.
12 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin baba rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan baba rẹ ni.
Mai wehe oe i kahi huna o ke kaikuwahine o kou makuakane, o ka io no ia o kou makuakane.
13 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin màmá rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan ìyá rẹ ni.
Mai wehe oe i kahi huna o ka hoahanau wahine o kou makuwahine; no ka mea, o ka io no ia o kou makuwahine.
14 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù arákùnrin baba rẹ nípa sísún mọ́ aya rẹ̀ láti bá a lòpọ̀ nítorí pé ìyàwó ẹ̀gbọ́n baba rẹ ni.
Mai wehe oe i kahi huna o ka hoahanaukane o kou makuakane, mai hookokoke aku i kana wahine, he makuwahine ia nou.
15 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọ àna obìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé aya ọmọ rẹ ni. Má ṣe bá a lòpọ̀.
Mai wehe oe i kahi huna o kau hunonawahine: o ka wahine ia a kau keiki: mai wehe oe i kona wahi huna.
16 “‘Má ṣe bá aya ẹ̀gbọ́n rẹ ọkùnrin lòpọ̀ nítorí pé yóò tàbùkù ẹ̀gbọ́n rẹ.
Mai wehe oe i kahi huna o ka wahine a kou hoahanaukane; o kahi huna ia o kou hoahanaukane.
17 “‘Má ṣe bá ìyá àti ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin ọmọkùnrin rẹ tàbí ọmọbìnrin ọmọbìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan rẹ tímọ́tímọ́ ni: nítorí àbùkù ni.
Mai wehe oe i kahi huna o ka wahine a me kana kaikamahine, aole hoi oe e lawe i ke kaikamahine a kana keiki, aole hoi i ke kaikamahine a kana kaikamahine, e wehe i kona wahi huna; o kona io no lakou; he mea hewa ia.
18 “‘Má ṣe fẹ́ àbúrò ìyàwó rẹ obìnrin ní aya gẹ́gẹ́ bí orogún tàbí bá a lòpọ̀, nígbà tí ìyàwó rẹ sì wà láààyè.
Mai lawe oe i ka wahine me kona hoahanauwahine pu, e hoino ia ia, i ka wehe i kona wahi huna, i ka wa e ola ana kela.
19 “‘Má ṣe súnmọ́ obìnrin láti bá a lòpọ̀ nígbà tí ó bá ń ṣe nǹkan oṣù, nítorí àkókò àìmọ́ ni.
Aole hoi oe e hookokoke aku i ka wahine e wehe i kona wahi huna, i ka wa e hookaawaleia'i ia no kona haumia.
20 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá aya aládùúgbò rẹ lòpọ̀, kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Mai moe oe i ka wahine a kou hoalauna, e hoohaumia iho ia oe iho me ia.
21 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ rú ẹbọ lórí pẹpẹ sí òrìṣà Moleki, kí o sì tipa bẹ́ẹ̀ ba orúkọ Ọlọ́run rẹ jẹ́. Èmi ni Olúwa.
Mai haawi i kahi keiki au e lilo ia Moleka, aole hoi oe e hoino i ka inoa o kou Akua: owau no Iehova.
22 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọkùnrin lòpọ̀ bí ìgbà tí ènìyàn ń bá obìnrin lòpọ̀: ìríra ni èyí jẹ́.
Mai moe i ke kanaka, me he wahine la: he mea ia e inainaia.
23 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ẹranko lòpọ̀ kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́. Obìnrin kò sì gbọdọ̀ jọ̀wọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ fún ẹranko láti bá a lòpọ̀, ohun tó lòdì ni.
Aole hoi oe e moe i ka holoholona, e hoohaumia iho ia oe iho me ia; aole hoi e ku ka wahine imua o ka holoholona e moe iho ia ia; he mea haumia hilahila ia.
24 “‘Má ṣe fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ba ara rẹ jẹ́, torí pé nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé kúrò níwájú yín ti ba ara wọn jẹ́.
Mai hoohaumia oukou ia oukou iho ma kekahi o keia mau mea, no ka mea, ma keia mau mea a pau ua haumia na lahuikanaka a'u e kipaku aku ai mai mua aku o oukou.
25 Nítorí pé ilẹ̀ náà di àìmọ́ nítorí náà mo fi ìyà jẹ ẹ́ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Ilẹ̀ náà sì pọ àwọn olùgbé ibẹ̀ jáde.
Ua haumia ka aina; nolaila, ke hoopai nei au i kona hewa maluna iho ona, a ke luai aku nei no ka aina i kona poe kamaaina.
26 Ṣùgbọ́n kí ẹ máa pa àṣẹ àti òfin mi mọ́. Onílé tàbí àjèjì tó ń gbé láàrín yín kò gbọdọ̀ ṣe ọ̀kan nínú àwọn ohun ìríra wọ̀nyí.
No ia mea, e malama oukou i ka'u mau kauoha a me ko'u mau kanawai, aole hoi e hana i kekahi o keia mau mea e inainaia, aole kekahi o ko oukou lahuikauaka, aole hoi o ka malihini e noho ana iwaena o oukou:
27 Nítorí pé gbogbo ohun ìríra wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ti gbé ilẹ̀ náà ṣáájú yín ti ṣe tí ó sì mú kí ilẹ̀ náà di aláìmọ́.
(No ka mea, ua hana na kanaka o ka aina mamua o oukou, i keia mau mea inainaia a pau, a ua haumia ka aina; )
28 Bí ẹ bá sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́ yóò pọ̀ yín jáde bí ó ti pọ àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ti wá ṣáájú yín jáde.
I ole ai e luai aku ka aina ia oukou kekahi, i ka wa e hoohaumia ai oukou ia ia, e like me kona luai ana'ku i na lahuikanaka, ka poe mamua o oukou.
29 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe ohun ìríra wọ̀nyí, kí ẹ gé irú ẹni náà kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
No ka mea o ka mea e hana i kekahi o keia mau mea inainaia, o na kanaka e hana, e okiia lakou maiwaena aku o ko lakou poe kanaka.
30 Nítorí náà ẹ gbọdọ̀ ṣe ohun tí mo fẹ́, kí ẹ má sì lọ́wọ́ nínú àṣà ìríra wọ̀nyí, tí wọn ń ṣe kí ẹ tó dé. Ẹ má ṣe fi wọ́n ba ara yín jẹ́. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Nolaila, e malama oukou i ka'u oihana, aole e hana ma keia mau hana inainaia, i hanaia mamua o oukou; aole hoi oukou e hoohaumia ia oukou iho malaila: owau no Iehova ko oukou Akua.

< Leviticus 18 >