< Leviticus 18 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé:
And the Lord spoke unto Moses, saying,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé: ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Speak unto the children of Israel, and say unto them, I am the Lord your God.
3 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní Ejibiti níbi tí ẹ ti gbé rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní ilẹ̀ Kenaani níbi tí èmi ń mú yín lọ. Ẹ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ìṣe wọn.
After the doings of the Land of Egypt, wherein ye have dwelt, shall ye not do; and after the doings of the land of Canaan whither I am bringing you, shall ye not do; and in their customs shall ye not walk.
4 Kí ẹ̀yin kí ó sì máa ṣe òfin mi, kí ẹ̀yin sì máa pa ìlànà mi mọ́, láti máa rìn nínú wọn, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
My ordinances shall ye do, and my statutes shall ye keep, to walk therein: I am the Lord your God.
5 Ẹ̀yin ó sì máa pa ìlànà mi mọ́ àti òfin mi; Ẹni tí ó ba ṣe, yóò yè nípa wọn. Èmi ni Olúwa.
And ye shall keep my statutes, and my ordinances, which if a man do, he shall live in them: I am the Lord.
6 “‘Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ súnmọ́ ìbátan rẹ̀ láti bá a lòpọ̀. Èmí ni Olúwa.
None of you shall approach to any that are near of kin to him, to uncover their nakedness: I am the Lord.
7 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyá rẹ lòpọ̀, ìyá rẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ bá a lòpọ̀.
The nakedness of thy father, or the nakedness of thy mother, shalt thou not uncover: she is thy mother, thou shalt not uncover her nakedness.
8 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyàwó baba rẹ lòpọ̀, nítorí ìhòhò baba rẹ ni.
The nakedness of thy father's wife shalt thou not uncover: it is thy father's nakedness.
9 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin rẹ tí ó jẹ́ ọmọ ìyá rẹ lòpọ̀, yálà a bí i nílé yín tàbí lóde.
The nakedness of thy sister, the daughter of thy father, or the daughter of thy mother, whether she be born at home, or born abroad, —even the nakedness of any of these shalt thou not uncover.
10 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin, ọmọ rẹ ọkùnrin lòpọ̀ tàbí ọmọbìnrin ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀ nítorí pé ìhòhò wọn, ìhòhò ìwọ fúnra rẹ̀ ni.
The nakedness of thy son's daughter, or of thy daughter's daughter, —even the nakedness of any of these, shalt thou not uncover; for theirs is thy own nakedness.
11 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin aya baba rẹ lòpọ̀; èyí tí a bí fún baba rẹ nítorí pé arábìnrin rẹ ni.
The nakedness of thy father's wife's daughter, begotten of thy father, she is thy sister, —thou shalt not uncover her nakedness.
12 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin baba rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan baba rẹ ni.
The nakedness of thy father's sister shalt thou not uncover: she is thy father's near kinswoman.
13 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin màmá rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan ìyá rẹ ni.
The nakedness of thy mother's sister shalt thou not uncover; for she is thy mother's near kinswoman.
14 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù arákùnrin baba rẹ nípa sísún mọ́ aya rẹ̀ láti bá a lòpọ̀ nítorí pé ìyàwó ẹ̀gbọ́n baba rẹ ni.
The nakedness of thy father's brother shalt thou not uncover: his wife shalt thou not approach, she is thy aunt.
15 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọ àna obìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé aya ọmọ rẹ ni. Má ṣe bá a lòpọ̀.
The nakedness of thy daughter-in-law shalt thou not uncover: she is thy son's wife, thou shalt not uncover her nakedness.
16 “‘Má ṣe bá aya ẹ̀gbọ́n rẹ ọkùnrin lòpọ̀ nítorí pé yóò tàbùkù ẹ̀gbọ́n rẹ.
The nakedness of thy brother's wife shalt thou not uncover: it is thy brother's nakedness.
17 “‘Má ṣe bá ìyá àti ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin ọmọkùnrin rẹ tàbí ọmọbìnrin ọmọbìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan rẹ tímọ́tímọ́ ni: nítorí àbùkù ni.
The nakedness of a woman and her daughter shalt thou not uncover: her son's daughter, or her daughter's daughter shalt thou not take, to uncover her nakedness; for they are near kinswomen; it is incest.
18 “‘Má ṣe fẹ́ àbúrò ìyàwó rẹ obìnrin ní aya gẹ́gẹ́ bí orogún tàbí bá a lòpọ̀, nígbà tí ìyàwó rẹ sì wà láààyè.
And a woman together with her sister shalt thou not take, to vex her, to uncover her nakedness, beside the other, in her lifetime.
19 “‘Má ṣe súnmọ́ obìnrin láti bá a lòpọ̀ nígbà tí ó bá ń ṣe nǹkan oṣù, nítorí àkókò àìmọ́ ni.
And a woman in the separation of her uncleanness shalt thou not approach, to uncover her nakedness.
20 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá aya aládùúgbò rẹ lòpọ̀, kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́ pẹ̀lú rẹ̀.
And with thy neighbor's wife shalt thou not lie carnally, to defile thyself with her.
21 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ rú ẹbọ lórí pẹpẹ sí òrìṣà Moleki, kí o sì tipa bẹ́ẹ̀ ba orúkọ Ọlọ́run rẹ jẹ́. Èmi ni Olúwa.
And any of thy seed shalt thou not let pass through [the fire] to Molech, and thou shalt not profane the name of thy God: I am the Lord.
22 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọkùnrin lòpọ̀ bí ìgbà tí ènìyàn ń bá obìnrin lòpọ̀: ìríra ni èyí jẹ́.
And with a man shalt thou not lie, as with a woman: it is an abomination.
23 “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ẹranko lòpọ̀ kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́. Obìnrin kò sì gbọdọ̀ jọ̀wọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ fún ẹranko láti bá a lòpọ̀, ohun tó lòdì ni.
And with any beast shalt thou not lie to defile thyself therewith; neither shall any woman stand before a beast to lie down thereto: it is confusion.
24 “‘Má ṣe fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ba ara rẹ jẹ́, torí pé nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé kúrò níwájú yín ti ba ara wọn jẹ́.
Do not defile yourselves through any of these things.; for through all these have become defiled the nations which I cast out before you:
25 Nítorí pé ilẹ̀ náà di àìmọ́ nítorí náà mo fi ìyà jẹ ẹ́ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Ilẹ̀ náà sì pọ àwọn olùgbé ibẹ̀ jáde.
And the land became defiled; wherefore I have visited its iniquity upon it, and the land itself vomited out its inhabitants.
26 Ṣùgbọ́n kí ẹ máa pa àṣẹ àti òfin mi mọ́. Onílé tàbí àjèjì tó ń gbé láàrín yín kò gbọdọ̀ ṣe ọ̀kan nínú àwọn ohun ìríra wọ̀nyí.
Ye shall therefore keep my statutes and my ordinances, and ye shall not commit any of these abominations; neither any of your own nation, nor the stranger that sojourneth among you;
27 Nítorí pé gbogbo ohun ìríra wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ti gbé ilẹ̀ náà ṣáájú yín ti ṣe tí ó sì mú kí ilẹ̀ náà di aláìmọ́.
(For all these abominations have the men of the land done, who were before you, and the land hath become defiled; )
28 Bí ẹ bá sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́ yóò pọ̀ yín jáde bí ó ti pọ àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ti wá ṣáájú yín jáde.
That the land may not vomit you out also, when ye defile it, as it hath vomited out the nations that were before you.
29 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe ohun ìríra wọ̀nyí, kí ẹ gé irú ẹni náà kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
For whosoever shall commit any of these abominations, — even the souls that commit them shall be cut off from among their people.
30 Nítorí náà ẹ gbọdọ̀ ṣe ohun tí mo fẹ́, kí ẹ má sì lọ́wọ́ nínú àṣà ìríra wọ̀nyí, tí wọn ń ṣe kí ẹ tó dé. Ẹ má ṣe fi wọ́n ba ara yín jẹ́. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Therefore shall ye keep my charge, so that ye commit not any one of these abominable customs, which were committed before you, and that ye do not defile yourselves therewith: I am the Lord your God.

< Leviticus 18 >