< Leviticus 17 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och HERREN talade till Mose och sade:
2 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli: ‘Ohun tí Olúwa pàṣẹ nìyí,
Tala till Aron och hans söner och alla Israels barn och säg till dem Detta är vad HERREN har bjudit och sagt:
3 bí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé Israẹli bá pa màlúù tàbí ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí àgbò nínú ibùdó tàbí bí ó bá pa á lẹ́yìn ibùdó
Om någon av Israels hus, i lägret eller utanför lägret, slaktar ett fäkreatur eller ett lamm eller en get,
4 tí kò sì mú un wá sí ibi àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa níwájú àgọ́ ìpàdé, ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni kí ẹ kà sí ẹni náà lọ́rùn: torí pé ó ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹni náà ni a ó sì gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
utan att föra fram djuret till uppenbarelsetältets ingång för att frambära det såsom en offergåva åt HERREN framför HERRENS tabernakel, så skall detta tillräknas den mannen såsom blodskuld, ty blod har han utgjutit, och den mannen skall utrotas ur sitt folk.
5 Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ Israẹli le è máa mú ẹbọ wọn tí wọn ti rú ní ìta gbangba wá sí iwájú Olúwa: wọ́n gbọdọ̀ mú un wá síwájú àlùfáà àní sí Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì rú wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa.
Därför skola Israels barn föra sina slaktdjur, som de pläga slakta ute på marken, fram till HERREN, till uppenbarelsetältets ingång, till prästen, och där slakta dem såsom tackoffer åt HERREN.
6 Àlùfáà náà yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ náà wọ́n ibi pẹpẹ Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, yóò sì sun ọ̀rá rẹ̀ ní òórùn dídùn sí Olúwa.
Och prästen skall stänka blodet på HERRENS altare, vid ingången till uppenbarelsetältet, och förbränna fettet till en välbehaglig lukt för HERREN.
7 Nítorí náà, kí wọn má ṣe rú ẹbọ wọn sí ère ẹranko mọ́, nínú èyí tí wọ́n ti ṣe àgbèrè tọ̀ lọ. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé láti ìran dé ìran wọn tí ń bọ̀.’
Och de skola icke mer offra sina slaktoffer åt de onda andar som de i trolös avfällighet löpa efter. Detta skall vara en evärdlig stadga för dem från släkte till släkte.
8 “Kí ó sọ fún wọn pé, ‘Ọkùnrin yówù kí ó jẹ́ ní ìdílé Israẹli tàbí ti àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn tí ó bá rú ẹbọ sísun tàbí ṣe ẹbọ
Och du skall säga till dem: Om någon av Israels hus, eller av främlingarna som bo ibland dem, offrar ett brännoffer eller ett slaktoffer
9 tí kò sì mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
och icke för det fram till uppenbarelsetältets ingång för att offra det åt HERREN, så skall den mannen utrotas ur sin släkt.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀ yálà nínú ìdílé Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni náà tí ó jẹ ẹ̀jẹ̀, èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Och om någon av Israels hus, eller av främlingarna som bo ibland dem, förtär något blod, så skall jag vända mitt ansikte mot honom som förtär blodet och utrota honom ur hans folk.
11 Nítorí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí ẹ̀dá wà, èmi sì ti fi fún yín lórí pẹpẹ fún ètùtù ọkàn yín: nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni a fi ń ṣe ètùtù fún ẹ̀mí ènìyàn.
Ty allt kötts själ är i blodet, och jag har givit eder det till altaret, till att bringa försoning för edra själar; ty blodet är det som bringar försoning, genom själen som är däri.
12 Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ọ̀kankan nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àlejò kan tí ń ṣe àtìpó nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀.
Därför säger jag till Israels barn: Ingen av eder skall förtära blod; och främlingen som bor ibland eder skall icke heller förtära blod.
13 “‘Ẹnikẹ́ni yálà nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé láàrín wọn, tí ó bá pa ẹranko tàbí ẹyẹ tí ó yẹ fún jíjẹ gbọdọ̀ ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ kí ó sì bò ó mọ́lẹ̀.
Och om någon av Israels barn, eller av främlingarna som bo ibland dem, fäller ett villebråd av fyrfotadjur eller en fågel, sådant som får ätas, så skall han låta blodet rinna ut och övertäcka det med jord.
14 Torí pé ẹ̀mí gbogbo ẹ̀dá ni ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, torí náà ni mo fi kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí kankan, torí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí wọ̀nyí ni ẹ̀mí wọn wà, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó gé kúrò.
Ty så är det med allt kötts själ, att blodet är det som innehåller själen; därför säger jag till Israels barn: I skolen icke förtära något kötts blod. Ty blodet är allt kötts själ; var och en som förtär det skall utrotas.
15 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó kú sílẹ̀ fúnra rẹ̀, tàbí èyí tí ẹranko búburú pa kálẹ̀ yálà onílé tàbí àlejò, ó ní láti fọ aṣọ rẹ̀. Kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di àṣálẹ́ lẹ́yìn èyí ni yóò tó di mímọ́.
Och var och en som äter ett självdött eller ihjälrivet djur, evad han är inföding eller främling, skall två sina kläder och bada sig i vatten och vara oren ända till aftonen; då bliver han ren.
16 Ṣùgbọ́n bí ó bá kọ̀ láti wẹ ara rẹ̀ tí kò sì fọ aṣọ rẹ̀ náà: ẹ̀bi rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.’”
Men om han icke tvår sina kläder och icke badar sin kropp kommer han att bära på missgärning.

< Leviticus 17 >