< Leviticus 17 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, zicând:
2 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli: ‘Ohun tí Olúwa pàṣẹ nìyí,
Vorbește lui Aaron și fiilor săi și tuturor copiilor lui Israel și spune-le: Acesta este lucrul pe care DOMNUL l-a poruncit spunând:
3 bí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé Israẹli bá pa màlúù tàbí ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí àgbò nínú ibùdó tàbí bí ó bá pa á lẹ́yìn ibùdó
Orice bărbat din casa lui Israel, care înjunghie un bou sau miel sau capră, în tabără, sau îl înjunghie în afara taberei,
4 tí kò sì mú un wá sí ibi àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa níwájú àgọ́ ìpàdé, ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni kí ẹ kà sí ẹni náà lọ́rùn: torí pé ó ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹni náà ni a ó sì gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Și nu îl aduce la ușa tabernacolului întâlnirii, pentru a aduce un dar DOMNULUI înaintea tabernacolului DOMNULUI, sânge să i se impute acelui bărbat; el a vărsat sânge; și acel bărbat să fie stârpit din mijlocul poporului său;
5 Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ Israẹli le è máa mú ẹbọ wọn tí wọn ti rú ní ìta gbangba wá sí iwájú Olúwa: wọ́n gbọdọ̀ mú un wá síwájú àlùfáà àní sí Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì rú wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa.
Pentru ca acești copii ai lui Israel să își aducă sacrificiile, pe care le aduce în câmp deschis, da, ca ei să le aducă DOMNULUI, la ușa tabernacolului întâlnirii, la preot și să le ofere ca ofrande de pace DOMNULUI.
6 Àlùfáà náà yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ náà wọ́n ibi pẹpẹ Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, yóò sì sun ọ̀rá rẹ̀ ní òórùn dídùn sí Olúwa.
Și preotul să stropească sângele peste altarul DOMNULUI la ușa tabernacolului întâlnirii și să ardă grăsimea pentru o aromă dulce DOMNULUI.
7 Nítorí náà, kí wọn má ṣe rú ẹbọ wọn sí ère ẹranko mọ́, nínú èyí tí wọ́n ti ṣe àgbèrè tọ̀ lọ. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé láti ìran dé ìran wọn tí ń bọ̀.’
Iar ei să nu mai aducă sacrificiile lor dracilor, după care au curvit. Acesta să le fie un statut pentru totdeauna prin toate generațiile lor.
8 “Kí ó sọ fún wọn pé, ‘Ọkùnrin yówù kí ó jẹ́ ní ìdílé Israẹli tàbí ti àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn tí ó bá rú ẹbọ sísun tàbí ṣe ẹbọ
Și să le spui: Orice bărbat din casa lui Israel, sau dintre străinii care locuiesc temporar printre voi, care aduce ofrandă arsă sau un sacrificiu,
9 tí kò sì mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Și nu îl aduce la ușa tabernacolului întâlnirii, pentru a-l oferi DOMNULUI, chiar acel bărbat să fie stârpit din mijlocul poporului său.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀ yálà nínú ìdílé Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni náà tí ó jẹ ẹ̀jẹ̀, èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Și orice bărbat din casa lui Israel, sau dintre străinii care locuiesc temporar printre voi, care mănâncă orice fel de sânge; chiar eu îmi voi întoarce fața împotriva acelui suflet care mănâncă sânge și îl voi stârpi din mijlocul poporului său.
11 Nítorí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí ẹ̀dá wà, èmi sì ti fi fún yín lórí pẹpẹ fún ètùtù ọkàn yín: nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni a fi ń ṣe ètùtù fún ẹ̀mí ènìyàn.
Pentru că viața cărnii este în sânge; și vi l-am dat pe altar pentru a se face ispășire pentru sufletele voastre, pentru că sângele este cel ce face ispășire pentru suflet.
12 Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ọ̀kankan nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àlejò kan tí ń ṣe àtìpó nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀.
De aceea am spus copiilor lui Israel: Niciun suflet dintre voi să nu mănânce sânge, nici vreun străin care locuiește temporar printre voi să nu mănânce sânge.
13 “‘Ẹnikẹ́ni yálà nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé láàrín wọn, tí ó bá pa ẹranko tàbí ẹyẹ tí ó yẹ fún jíjẹ gbọdọ̀ ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ kí ó sì bò ó mọ́lẹ̀.
Și orice bărbat dintre copiii lui Israel, sau dintre străinii care locuiesc temporar printre voi, care vânează și prinde orice fiară sau pasăre care poate fi mâncată, chiar el să îi scurgă sângele și să îl acopere cu țărână.
14 Torí pé ẹ̀mí gbogbo ẹ̀dá ni ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, torí náà ni mo fi kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí kankan, torí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí wọ̀nyí ni ẹ̀mí wọn wà, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó gé kúrò.
Pentru că el este viața întregii cărni; sângele acesteia este pentru viața ei; de aceea am spus copiilor lui Israel: Să nu mâncați sânge de la niciun fel de carne, pentru că viața întregii cărni este sângele ei, oricine îl mănâncă să fie stârpit!
15 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó kú sílẹ̀ fúnra rẹ̀, tàbí èyí tí ẹranko búburú pa kálẹ̀ yálà onílé tàbí àlejò, ó ní láti fọ aṣọ rẹ̀. Kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di àṣálẹ́ lẹ́yìn èyí ni yóò tó di mímọ́.
Și fiecare suflet care mănâncă ceea ce a murit de la sine, sau care a fost sfâșiat de fiare, fie unul din țara voastră, sau un străin, deopotrivă să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara, apoi să fie curat.
16 Ṣùgbọ́n bí ó bá kọ̀ láti wẹ ara rẹ̀ tí kò sì fọ aṣọ rẹ̀ náà: ẹ̀bi rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.’”
Dar dacă nu le spală, nici nu își îmbăiază carnea, atunci să își poarte propria nelegiuire.

< Leviticus 17 >