< Leviticus 17 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Angraeng mah Mosi khaeah,
2 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli: ‘Ohun tí Olúwa pàṣẹ nìyí,
Aaron hoi a capanawk, Israel kaminawk boih khaeah, Angraeng mah hae tiah thuih;
3 bí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé Israẹli bá pa màlúù tàbí ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí àgbò nínú ibùdó tàbí bí ó bá pa á lẹ́yìn ibùdó
kawbaktih Israel kami mah doeh maitaw maeto, to tih ai boeh loe tuucaa maeto, to tih ai boeh loe maeh to angmacae ohhaih im ah maw, to tih ai boeh loe tasa bangah maw boh moe,
4 tí kò sì mú un wá sí ibi àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa níwájú àgọ́ ìpàdé, ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni kí ẹ kà sí ẹni náà lọ́rùn: torí pé ó ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹni náà ni a ó sì gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Angraeng ih kahni im hmaa ih, amkhuenghaih kahni im thok taengah, Angraeng khaeah paek han sin ai nahaeloe, to kami to athii longsak kami ah net moe, angmah ih acaeng thung hoi pahnawt han oh.
5 Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ Israẹli le è máa mú ẹbọ wọn tí wọn ti rú ní ìta gbangba wá sí iwájú Olúwa: wọ́n gbọdọ̀ mú un wá síwájú àlùfáà àní sí Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì rú wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa.
Israel kaminawk loe taw ah a sak o ih angbawnhaih to, kaminawk amkhuenghaih kahni im hmaa, Angraeng hmaa ah, qaima khaeah sin o tih; to hmuen to Angraeng khaeah angdaeh angbawnhaih ahmuen ah paek o tih.
6 Àlùfáà náà yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ náà wọ́n ibi pẹpẹ Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, yóò sì sun ọ̀rá rẹ̀ ní òórùn dídùn sí Olúwa.
Qaima mah athii to amkhuenghaih kahni im thok taengah kaom, hmaicam nuiah haeh ueloe, Angraeng khaeah hmuihoih ah athawk to hmai pakhaem tih.
7 Nítorí náà, kí wọn má ṣe rú ẹbọ wọn sí ère ẹranko mọ́, nínú èyí tí wọ́n ti ṣe àgbèrè tọ̀ lọ. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé láti ìran dé ìran wọn tí ń bọ̀.’
Nihcae mah angmacae hoi a takpum zawhhaih, taqawk khaeah angbawnhaih sah o mak ai boeh. Hae loe nihcae hoi a caanawk khoek to pazui han paek ih dungzan ah kaom zaehhoihhaih daan ah oh.
8 “Kí ó sọ fún wọn pé, ‘Ọkùnrin yówù kí ó jẹ́ ní ìdílé Israẹli tàbí ti àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn tí ó bá rú ẹbọ sísun tàbí ṣe ẹbọ
Nihcae khae ih, Mi kawbaktih Israel kami doeh, nihcae khaeah kaom angvinnawk doeh, hmai angbawnhaih maw, to tih ai boeh loe paek han ih hmuen maw a sin o naah,
9 tí kò sì mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
amkhuenghaih kahni im thok taengah, Angraeng khaeah sin o ai nahaeloe, to kami to angmah ih acaeng thung hoi pahnawt oh, tiah thui paeh.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀ yálà nínú ìdílé Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni náà tí ó jẹ ẹ̀jẹ̀, èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Israel imthung takoh mah maw, to tih ai boeh loe nihcae salakah kaom angvinnawk mah maw, athii to caa o nahaeloe, athii caa kami to mikhmai ka set thuih moe, angmah ih acaeng thung hoiah pahnawt sut han.
11 Nítorí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí ẹ̀dá wà, èmi sì ti fi fún yín lórí pẹpẹ fún ètùtù ọkàn yín: nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni a fi ń ṣe ètùtù fún ẹ̀mí ènìyàn.
Taksa hinghaih loe athii thungah oh; na sak o ih zaehaih to tahmen moe, na hing o thai hanah, to athii to hmaicam nuiah ka paek boeh; hae loe kami hing hanah zae angbawnhaih athii ah oh.
12 Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ọ̀kankan nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àlejò kan tí ń ṣe àtìpó nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀.
To pongah Israel kaminawk khaeah, Nangcae thung ih mi kawbaktih doeh athii to caa o hmah; nangcae salakah kaom angvin mah doeh athii to caak han om ai, tiah ka thuih boeh.
13 “‘Ẹnikẹ́ni yálà nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé láàrín wọn, tí ó bá pa ẹranko tàbí ẹyẹ tí ó yẹ fún jíjẹ gbọdọ̀ ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ kí ó sì bò ó mọ́lẹ̀.
Israel kami mah maw, to tih ai boeh loe nangcae salakah kaom angvin mah maw, moi zoep naah moi maw, tavaa maw naeh nahaeloe, athii pathok moe, athii to maiphu hoi aphum pacoengah ni, caak han oh.
14 Torí pé ẹ̀mí gbogbo ẹ̀dá ni ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, torí náà ni mo fi kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí kankan, torí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí wọ̀nyí ni ẹ̀mí wọn wà, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó gé kúrò.
Athii loe taksa boih hinghaih ah oh; to pongah, Nangcae loe kawbaktih moi thii doeh caa o hmah, tiah Israel kaminawk khaeah ka thuih boeh; taksa boih hinghaih loe athii ah oh pongah, athii caa kami loe, pahnawt sut ah om tih.
15 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó kú sílẹ̀ fúnra rẹ̀, tàbí èyí tí ẹranko búburú pa kálẹ̀ yálà onílé tàbí àlejò, ó ní láti fọ aṣọ rẹ̀. Kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di àṣálẹ́ lẹ́yìn èyí ni yóò tó di mímọ́.
Angmah koeh kadueh moi, moi kasan mah kaek ih moi caa kami, prae thung ih kami maw, to tih ai boeh loe angvin doeh, a khukbuen to pasuk moe, tui amhluk han oh; anih loe duembang khoek to ciim mak ai; tui amhluk pacoengah ni ciim vop tih.
16 Ṣùgbọ́n bí ó bá kọ̀ láti wẹ ara rẹ̀ tí kò sì fọ aṣọ rẹ̀ náà: ẹ̀bi rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.’”
Toe a khukbuen to pasuk ai moe, tui doeh amhluh ai nahaeloe, to kami loe a zaehaih tho to hnu tih, tiah thui paeh, tiah a naa.

< Leviticus 17 >