< Leviticus 16 >

1 Olúwa sọ fún Mose lẹ́yìn ikú àwọn ọmọ Aaroni méjèèjì tí wọ́n kú nígbà tí wọ́n súnmọ́ Olúwa.
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise după moartea celor doi fii ai lui Aaron, când au oferit înaintea DOMNULUI și au murit.
2 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Kìlọ̀ fún Aaroni arákùnrin rẹ pé kí ó má ṣe máa wá nígbà gbogbo sí Ibi Mímọ́ Jùlọ tí ó wà lẹ́yìn aṣọ títa ní ibi tí àpótí ẹ̀rí àti ìtẹ́ àánú wà, kí ó má ba à kú nítorí pé Èmi ó farahàn nínú ìkùùkuu lórí ìtẹ́ àánú.
Și DOMNUL i-a zis lui Moise: Spune-i lui Aaron, fratele tău, să nu vină tot timpul în locul sfânt dinăuntrul perdelei, care este înaintea șezământului milei de deasupra chivotului, ca să nu moară, pentru că eu voi apărea în norul de peste șezământul milei.
3 “Báyìí ni Aaroni yóò ṣe máa wá sí Ibi Mímọ́ Jùlọ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti àgbò fún ẹbọ sísun.
Astfel să vină Aaron în locul sfânt, cu un taur tânăr ca ofrandă pentru păcat, și cu un berbec ca ofrandă arsă.
4 Òun yóò sì wọ aṣọ funfun mímọ́ pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ funfun, yóò sì fi àmùrè funfun mímọ́ dì í, yóò sì dé fìlà funfun, àwọn aṣọ mímọ́ nìwọ̀nyí. Òun yóò sì fi omi wẹ̀, kí ó tó wọ̀ wọ́n.
Să îmbrace tunica sfântă de in și să aibă izmenele de in peste carnea sa și să fie încins cu un brâu de in și cu mitra de in să fie împodobit, acestea sunt sfintele veștminte; de aceea să își spele carnea în apă și astfel să le îmbrace.
5 Òun yóò sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì láti ọ̀dọ̀ gbogbo àgbájọpọ̀ àwọn ọmọ Israẹli láti fi ṣe ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wọ́n, àti àgbò kan fún ẹbọ sísun.
Și să ia din adunarea copiilor lui Israel doi iezi dintre capre, ca ofrandă pentru păcat, și un berbec ca ofrandă arsă.
6 “Aaroni yóò sì fi akọ màlúù rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ èyí tí ṣe ti ara rẹ̀ òun yóò sì ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀.
Și Aaron să aducă taurul său al ofrandei pentru păcat, care este pentru el, și să facă ispășire pentru el și pentru casa lui.
7 Lẹ́yìn náà yóò sì mú ewúrẹ́ méjì náà wá sí iwájú Olúwa ní ibi ìlẹ̀kùn àgọ́ ìpàdé.
Și să ia cei doi țapi și să îi prezinte înaintea DOMNULUI la ușa tabernacolului întâlnirii.
8 Aaroni yóò sì dìbò ní ti àwọn ewúrẹ́ méjèèjì náà, ìbò àkọ́kọ́ fún ti Olúwa, àti èkejì fún ewúrẹ́ ìpààrọ̀.
Și Aaron să arunce sorții peste cei doi țapi, un sorț pentru DOMNUL și celălalt sorț pentru țapul ispășitor.
9 Aaroni yóò sì mú ewúrẹ́ tí ìbò Olúwa mú, yóò sì fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Și Aaron să aducă țapul peste care a căzut sorțul DOMNULUI și să îl ofere ca ofrandă pentru păcat.
10 Ṣùgbọ́n ewúrẹ́ tí ìbò bá mú gẹ́gẹ́ bí ewúrẹ́ ìpààrọ̀ ni a ó mú wá láààyè síwájú Olúwa láti fi ṣe ètùtù sí i àti láti jẹ́ kí ó lọ lọ́fẹ̀ẹ́, sí aginjù.
Dar țapul peste care a căzut sorțul să fie țap ispășitor, să fie prezentat viu înaintea DOMNULUI, să facă ispășire cu el și pentru a-l lăsa să plece în pustie, ca țap ispășitor.
11 “Aaroni yóò sì mú akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wá láti ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀. Yóò sì pa akọ màlúù náà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tirẹ̀.
Și Aaron să aducă taurul ofrandei pentru păcat, care este pentru el, și să facă ispășire pentru el și pentru casa lui, și să înjunghie taurul ofrandei pentru păcat, care este pentru el;
12 Yóò sì mú àwo tùràrí tí ó kún fún èédú tí a ti sun pẹ̀lú iná láti orí pẹpẹ wá síwájú Olúwa: àti ẹ̀kúnwọ́ méjì tùràrí tí a gún kúnná yóò sì mú un wá sí ẹ̀yìn aṣọ títa.
Și să ia o tămâietoare plină cu cărbuni, arzând din focul de la altarul dinaintea DOMNULUI, și mâinile sale pline de tămâie dulce, zdrobită mărunt, și să le aducă înăuntrul perdelei;
13 Yóò sì fi tùràrí náà lé orí iná níwájú Olúwa: kí èéfín tùràrí náà ba à le bo ìtẹ́ àánú tí ó wà ní orí àpótí ẹ̀rí kí o má ba à kú.
Și să pună tămâia peste focul dinaintea DOMNULUI, ca norul tămâiei să acopere șezământul milei, care este deasupra mărturiei, ca el să nu moară;
14 Yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ ọmọ màlúù náà yóò sì fi ìka rẹ̀ wọ́n ọn, ní iwájú ìtẹ́ àánú, yóò sì fi ìka rẹ̀ wọ́n ọn nígbà méje níwájú ìtẹ́ àánú.
Și să ia din sângele taurului și să îl stropească cu degetul său peste șezământul milei înspre est; și să stropească cu degetul său de șapte ori, din sânge, înaintea șezământului milei.
15 “Nígbà yìí ni yóò pa ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó wà fún àwọn ènìyàn yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sí ẹ̀yìn aṣọ títa, bí ó ti ṣe ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà ni yóò ṣe ti ewúrẹ́ yìí, yóò sì wọ́n ọn sórí ìtẹ́ ètùtù àti síwájú ìtẹ́ ètùtù.
Apoi să înjunghie țapul ofrandei pentru păcat, care este pentru popor, și să aducă sângele lui înăuntrul perdelei și să facă cu acel sânge la fel cum a făcut cu sângele taurului, și să îl stropească peste șezământul milei și înaintea șezământului milei;
16 Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún Ibi Mímọ́ Jùlọ nítorí àìmọ́ àwọn ará Israẹli àti nítorí gbogbo ìrékọjá wọn àti ìṣọ̀tẹ̀ wọn nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbogbo, bákan náà ni yóò sì ṣe fún àgọ́ ìpàdé, èyí tí ó wà láàrín wọn nínú àìmọ́ wọn.
Și să facă ispășire pentru locul sfânt, din cauza necurățiilor copiilor lui Israel și din cauza fărădelegilor lor în toate păcatele lor, și astfel să facă pentru tabernacolul întâlnirii, care rămâne printre ei în mijlocul necurățiilor lor.
17 Kí ó má ṣe sí ẹyọ ènìyàn kan nínú àgọ́ ìpàdé nígbà tí òun bá wọ Ibi Mímọ́ Jùlọ lọ láti ṣe ètùtù, títí di ìgbà tí yóò fi jáde lẹ́yìn tí ó ba ṣe ètùtù fúnra rẹ̀ fún ìdílé rẹ̀ àti fún gbogbo àgbájọpọ̀ Israẹli.
Și să nu fie niciun om în tabernacolul întâlnirii când intră el, pentru a face ispășire în locul sfânt, până când iese și până când nu a făcut ispășire pentru el și pentru casa sa și pentru toată adunarea lui Israel.
18 “Lẹ́yìn náà òun yóò lọ sí ibi pẹpẹ tí ó wà níwájú Olúwa, yóò sì ṣe ètùtù fún pẹpẹ náà. Yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù àti nínú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà, yóò sì fi sí orí ọ̀kọ̀ọ̀kan ìwo pẹpẹ náà yíká.
Și să iasă la altarul, care este înaintea DOMNULUI, și să facă ispășire pentru el; și să ia din sângele taurului și din sângele țapului și să îl pună pe coarnele altarului de jur împrejur.
19 Lẹ́yìn náà, òun yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà sórí rẹ̀ pẹ̀lú ìka rẹ̀ nígbà méje láti wẹ̀ ẹ́ mọ́ àti láti sọ ọ́ dí mímọ́ kúrò nínú àìmọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
Și să stropească din sânge peste acesta cu degetul său, de șapte ori, și să îl curețe și să îl sfințească de necurățiile copiilor lui Israel.
20 “Lẹ́yìn ti Aaroni ti parí ṣíṣe ètùtù ti Ibi Mímọ́ Jùlọ, ti àgọ́ ìpàdé àti ti pẹpẹ, òun yóò sì mú ààyè ewúrẹ́ wá.
Și după ce a terminat cu împăcarea locului sfânt și a tabernacolului întâlnirii și a altarului, să aducă țapul viu;
21 Aaroni yóò sì gbé ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì lé orí ààyè ewúrẹ́ náà, yóò sì jẹ́wọ́ gbogbo ìwà búburú àti ìṣọ̀tẹ̀ àwọn ara Israẹli lé e lórí. Gbogbo ìrékọjá wọn àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn ni yóò sì gbé ka orí ewúrẹ́ náà. Yóò sì rán an lọ sí ijù láti ọwọ́ ẹni tí a yàn fún iṣẹ́ náà.
Și Aaron să își pună amândouă mâinile pe capul țapului viu și să mărturisească peste el toate nelegiuirile copiilor lui Israel, și toate fărădelegile lor în toate păcatele lor, punându-le pe capul țapului și să îl trimită să plece departe în pustie, prin mâna unui bărbat pregătit;
22 Ewúrẹ́ náà yóò sì ru gbogbo àìṣedéédéé wọn lọ sí ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé. Òun yóò sì jọ̀wọ́ ewúrẹ́ náà lọ́wọ́ lọ sínú ijù.
Și țapul să poarte pe el toate nelegiuirile lor într-un pământ nelocuit, și să lase țapul să plece în pustie.
23 “Aaroni yóò sì padà wá sí ibi àgọ́ ìpàdé, yóò sì bọ́ aṣọ ọ̀gbọ̀ wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, tí ó wọ̀ nígbà tí ó lọ sí Ibi Mímọ́ Jùlọ, yóò sì fi wọ́n sílẹ̀ níbẹ̀.
Și Aaron să intre în tabernacolul întâlnirii și să dezbrace veșmintele de in, pe care le-a îmbrăcat, când a intrat în locul sfânt, și să le lase acolo;
24 Yóò sì fi omi wẹ ara rẹ̀ ní ibi mímọ́ kan, yóò sì wọ aṣọ rẹ̀ yóò sì wá ṣí iwájú, yóò sì rú ẹbọ sísun ti ara rẹ̀ àti ẹbọ sísun ti àwọn ènìyàn láti ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti fún àwọn ènìyàn.
Și să își spele carnea cu apă în locul sfânt și să își îmbrace veșmintele și să iasă înainte și să aducă ofranda sa arsă și ofranda arsă a poporului, și să facă ispășire pentru el și pentru popor.
25 Òun yóò sì sun ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà lórí pẹpẹ.
Și grăsimea ofrandei pentru păcat o să ardă pe altar.
26 “Ẹni tí ó tú ewúrẹ́ ìpààrọ̀ náà sílẹ̀ yóò sì fọ aṣọ rẹ̀, yóò sì wẹ ara rẹ̀ nínú omi, lẹ́yìn èyí ó lè wá sí ibùdó.
Și cel ce a lăsat țapul să plece, țapul ispășitor, să își spele hainele și să își îmbăieze carnea în apă, și după aceea să intre în tabără.
27 Ọ̀dọ́ akọ màlúù àti ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tí a ti mú ẹ̀jẹ̀ wọn wá sí Ibi Mímọ́ Jùlọ ni kí a gbe jáde kúrò ní ibùdó. Awọ wọn ni a ó fi iná sun bákan náà.
Și taurul ca ofrandă pentru păcat și țapul ca ofrandă pentru păcat, al căror sânge a fost adus înăuntru pentru a se face ispășire în locul sfânt, de unul să fie duși afară din tabără, iar ei să ardă în foc pielea lor și carnea lor și balega lor.
28 Ẹni tí ó sun wọ́n yóò sì fọ aṣọ rẹ̀, yóò sì wẹ ara rẹ̀, lẹ́yìn èyí ni ó tó le wọ ibùdó.
Și cel ce le arde să își spele hainele și să își îmbăieze carnea în apă, și după aceea să intre în tabără.
29 “Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà títí láé fún un yín, pé ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ni ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan, yálà onílé tàbí àlejò tí ó ń gbé pẹ̀lú yín.
Și acesta să vă fie un statut pentru totdeauna, în luna a șaptea, în ziua a zecea a lunii, să vă chinuiți sufletele și să nu faceți deloc nicio lucrare, nici cel din țara voastră, nici străinul care locuiește temporar printre voi;
30 Torí pé ní ọjọ́ yìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún yín láti sọ yín di mímọ́, kí ẹ̀yin bá à le mọ́ níwájú Olúwa yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo.
Pentru că în ziua aceea preotul va face ispășire pentru voi, pentru a vă curăța ca să fiți curați de toate păcatele voastre înaintea DOMNULUI.
31 Ọjọ́ yìí yóò jẹ́ ọjọ́ ìsinmi pátápátá fún un yín, ẹ̀yin yóò sì ṣẹ́ ara yín. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé.
Aceasta să vă fie un sabat al odihnei și să vă chinuiți sufletele, printr-un statut pentru totdeauna.
32 Àlùfáà náà tí a ti fi òróró yàn tí a sì ti sọ di mímọ́ láti máa ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ilé ìsìn ní ipò baba rẹ̀, òun ni kí ó ṣe ètùtù, yóò sì wọ aṣọ funfun gbòò àní aṣọ mímọ́ náà, òun yóò sì ṣe ètùtù.
Și preotul, pe care el îl va unge și pe care îl va consacra pentru a servi în serviciul de preot în locul tatălui său, să facă ispășirea și să îmbrace veșmintele de in, veștmintele sfinte;
33 Yóò sì ṣe ètùtù fún Ibi Mímọ́ Jùlọ, fún ìpàdé àti fún pẹpẹ, yóò sì ṣe ètùtù fún àlùfáà àti fún gbogbo àgbájọpọ̀ àwọn ènìyàn náà.
Și să facă ispășire pentru sanctuarul sfânt și să facă ispășire pentru tabernacolul întâlnirii și pentru altar, și să facă ispășire pentru preoți și pentru tot poporul adunării.
34 “Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún yín: láti máa ṣe ètùtù fún àwọn ará Israẹli fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn lẹ́ẹ̀kan lọ́dún.” Ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Și acesta să vă fie un statut veșnic, pentru a face ispășire pentru copiii lui Israel pentru toate păcatele lor, o singură dată pe an. Iar el a făcut precum DOMNUL i-a poruncit lui Moise.

< Leviticus 16 >