< Leviticus 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Și DOMNUL le-a vorbit lui Moise și lui Aaron, zicând:
2 “Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí ẹ wí fún wọn pé, ‘Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara, ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́.
Vorbește copiilor lui Israel și spune-le: Când vreun bărbat are o scurgere din carnea lui, din cauza scurgerii lui, este necurat.
3 Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́:
Și aceasta să fie necurățenia lui, în scurgerea lui, fie carnea lui curge cu scurgerea lui, fie carnea lui este închisă de la scurgerea lui, aceasta este necurăția lui.
4 “‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́.
Fiecare pat, pe care se culcă cel ce are scurgerea, este necurat, și fiecare lucru, pe care șade el, să fie necurat.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Și oricine atinge patul lui să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara.
6 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și cel ce șade pe orice lucru pe care a șezut cel ce are scurgerea să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara.
7 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și cel ce atinge carnea celui ce are scurgerea să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara.
8 “‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și dacă cel ce are scurgerea scuipă peste cel ce este curat, atunci acela să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara.
9 “‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́.
Și orice șea, pe care călărește cel ce are scurgerea, să fie necurată.
10 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și oricine atinge orice lucru care a fost sub el, să fie necurat până seara, și cel ce va căra oricare din acele lucruri să își spele hainele și să se îmbăieze și să fie necurat până seara.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Și pe oricine atinge cel ce are scurgerea și nu și-a clătit mâinile sale în apă, să își spele hainele și să se îmbăieze și să fie necurat până seara.
12 “‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.
Și vasele de lut, pe care le-a atins cel ce are scurgerea, să fie sparte; și fiecare vas de lemn să fie clătit în apă.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì di mímọ́.
Și când cel ce are o scurgere este curățat de scurgerea sa, atunci el să își numere șapte zile pentru curățirea sa și să își spele hainele și să își îmbăieze carnea în apă curgătoare și să fie curat.
14 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà.
Și în ziua a opta să ia pentru el două turturele, sau doi porumbei tineri și să vină înaintea DOMNULUI la ușa tabernacolului întâlnirii și să le dea preotului;
15 Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.
Și preotul să le aducă, una ca ofrandă pentru păcat și cealaltă ca ofrandă arsă; și preotul să facă ispășire pentru el înaintea DOMNULUI, pentru scurgerea lui.
16 “‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀, kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Și dacă sămânța de împreunare a vreunui bărbat iese din el, atunci să își spele toată carnea în apă și să fie necurat până seara.
17 Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́.
Și fiecare haină și fiecare piele, pe care este sămânța de împreunare, să fie spălată cu apă și să fie necurată până seara.
18 Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀, kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
De asemenea femeia cu care bărbatul se va culca cu sămânța împreunării, amândoi să se îmbăieze în apă și să fie necurați până seara.
19 “‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀, obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Și dacă vreo femeie are o scurgere și scurgerea în carnea ei este sânge, să fie separată șapte zile, și oricine o atinge să fie necurat până seara.
20 “‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́.
Și fiecare lucru pe care ea se culcă în separarea ei să fie necurat; orice lucru pe care ea șade, de asemenea să fie necurat.
21 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și oricine îi atinge patul să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara.
22 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și oricine atinge orice lucru pe care ea a șezut să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara.
23 Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și dacă este ceva pe patul ei, sau vreun lucru pe care ea șade, când el îl atinge, să fie necurat până seara.
24 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.
Și dacă un bărbat se culcă cu ea și necurăția ei este peste el, să fie necurat șapte zile; și tot patul pe care el se culcă să fie necurat.
25 “‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
Și dacă o femeie are o scurgere din sângele ei multe zile, mai mult timp decât zilele separării ei; toate zilele scurgerii necurăției ei să fie la fel ca zilele separării ei, ea să fie necurată.
26 Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
Orice pat pe care se culcă în toate zilele scurgerii ei, să îi fie ca patul zilelor separării ei, și pe orice lucru se așază să fie necurat, ca necurăția separării ei.
27 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Și oricine atinge acele lucruri să fie necurat și să își spele hainele și să se îmbăieze în apă și să fie necurat până seara.
28 “‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́.
Dar dacă ea este curățată de scurgerea ei, atunci să își numere șapte zile și după aceea să fie curată.
29 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Și în ziua a opta să ia pentru ea două turturele, sau doi porumbei tineri și să îi aducă la preot, la ușa tabernacolului întâlnirii.
30 Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Și preotul să o aducă pe una ca ofrandă pentru păcat și pe cealaltă ca ofrandă arsă; și preotul să facă ispășire pentru ea înaintea DOMNULUI, pentru scurgerea necurăției ei.
31 “‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́, èyí tí ó wà láàrín wọn.’”
Astfel să separați pe copiii lui Israel de necurățiile lor; ca să nu moară în necurățiile lor, când ei spurcă tabernacolul meu care este între ei.
32 Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
Aceasta este legea celui ce are o scurgere și a aceluia căruia îi iese sămânța din el și este întinat de acestea;
33 Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.
Și a celei bolnave cu necurăția ei și a celui ce are o scurgere, a bărbatului sau a femeii și a celui ce se culcă cu cea care este necurată.

< Leviticus 15 >