< Leviticus 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Rzekł potem Pan do Mojżesza i do Aarona, mówiąc:
2 “Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí ẹ wí fún wọn pé, ‘Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara, ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́.
Powiedzcie synom Izraelskim, a mówcie do nich: Mąż, który by cierpiał płynienie nasienia z ciała swego, nieczysty jest.
3 Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́:
A tać będzie nieczystość płynienia jego: Jeźli wypuści ciało jego płynienie swe, albo żeby się to płynienie zastanowiło w ciele jego, nieczystość jego jest.
4 “‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́.
Każda pościel, na której by leżał płynienie cierpiący, nieczysta będzie, i wszystko, na czem by usiadł, nieczyste będzie.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Kto by się dotknął pościeli jego, upierze szaty swoje, i umyje się wodą, a będzie nieczystym aż do wieczora.
6 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Kto by też siadł na tem, na czem ten siedział, co z niego nasienie płynie, upierze szaty swe, i umyje się wodą, a będzie nieczystym aż do wieczora.
7 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Jeźliby się też kto dotknął ciała męża cierpiącego płynienie, upierze szaty swe, i umyje się wodą, a będzie nieczystym aż do wieczora.
8 “‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
A jeźliby plunął płynienie cierpiący na czystego, oplwany upierze szaty swe, i umyje się wodą, a będzie nieczysty aż do wieczora.
9 “‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́.
Każde też siodło, na którem by siedział płynienie cierpiący, nieczyste będzie.
10 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Kto by się też jakiejkolwiek rzeczy dotknął, która była po nim, nieczysty będzie aż do wieczora; a kto by co z tego nosił, upierze szaty swe, i umyje się wodą, a będzie nieczystym aż do wieczora.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Także każdy, którego by się dotknął cierpiący płynienie, nie umywszy przedtem rąk swoich w wodzie, upierze szaty swoje, i umyje się wodą, i będzie nieczystym aż do wieczora.
12 “‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.
Naczynie też gliniane, którego by się dotknął, co płynienie cierpi, stłuczone będzie, a każde naczynie drzewiane wodą umyte będzie.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì di mímọ́.
A gdyby oczyszczony był ten, który cierpi płynienie, od płynienia swego, naliczy sobie siedem dni podług swego oczyszczenia, i upierze szaty swe, i omyje ciało swoje wodą żywą, i będzie czystym.
14 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà.
Potem dnia ósmego weźmie sobie dwie synogarlice, albo dwoje gołąbiąt, a przyszedłszy przed Pana do drzwi namiotu zgromadzenia, odda je kapłanowi.
15 Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.
Tedy ofiarować będzie kapłan jedno z nich za grzech, a drugie na ofiarę całopalenia. Tak oczyści go kapłan przed obliczem Pańskiem od płynienia jego.
16 “‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀, kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
A mąż, z którego by wyszło nasienie złączenia, o myje wodą wszystko ciało swe, i będzie nieczystym aż do wieczora.
17 Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́.
Każda też szata, i każda skóra, na której by było nasienie złączenia, wyprana będzie wodą, a będzie nieczystą aż do wieczora.
18 Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀, kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Niewiasta także, z którą by obcował mąż cierpiący płynienie nasienia, oboje umyją się wodą, a nieczystymi będą aż do wieczora.
19 “‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀, obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Także niewiasta, która by cierpiała chorobę swoję, a płynęłaby krew z ciała jej, przez siedem dni będzie w odłączeniu swem; każdy, coby się jej dotknął, nieczysty będzie aż do wieczora.
20 “‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́.
Na czembykolwiek leżała w odłączeniu swem, nieczyste będzie; także na czem by siedziała, nieczyste będzie.
21 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Kto by się też dotknął pościeli jej, upierze szaty swe, i umyje się wodą, a będzie nieczysty aż do wieczora.
22 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Także kto by się dotknął tego, na czem by siedziała, upierze szaty swe, i umyje się wodą, a będzie nieczysty aż do wieczora.
23 Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Jeźliby też co było na łożu jej, albo na czem by ona siedziała, a dotknąłby się kto tego, nieczystym będzie aż do wieczora.
24 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.
A jeźliby mąż spał z nią, a zostałaby nieczystość jej na nim, nieczysty będzie przez siedem dni, i każde łoże, na którem by leżał, nieczyste będzie.
25 “‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
Jeźliby też niewiasta płynienie krwi cierpiała przez wiele dni, mimo czasu miesiąców jej, albo żeby krwi płynienie cierpiała w zwyczajnej chorobie, tedy po wszystkie dni płynienia nieczystości swojej, jako i czasu choroby swojej, nieczystą będzie.
26 Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
Każda pościel jej, na której by leżała po wszystkie dni płynienia swego, jako pościel w przyrodzonej chorobie będzie, i każda rzecz, na której by siedziała, nieczysta będzie według nieczystości przyrodzonej choroby jej.
27 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Kto by się kolwiek dotknął tych rzeczy, nieczystym będzie, i upierze szaty swe, i umyje się wodą, a będzie nieczystym aż do wieczora.
28 “‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́.
A gdy będzie oczyszczona od płynienia swego, naliczy sobie siedem dni, a potem oczyszczać się będzie.
29 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
A dnia ósmego weźmie sobie dwie synogarlice, albo dwoje gołąbiąt, i przyniesie je kapłanowi do drzwi namiotu zgromadzenia;
30 Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Z których ofiarować będzie kapłan, jedno na ofiarę za grzech, a drugie na ofiarę całopalenia: tak ją oczyści kapłan przed Panem od płynienia nieczystości jej.
31 “‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́, èyí tí ó wà láàrín wọn.’”
Tak odłączać będziecie syny Izraelskie od nieczystości ich, aby nie pomarli w nieczystości swej, gdyby splugawili przybytek mój, który jest w pośrodku ich.
32 Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
Tać jest ustawa około tego, który płynienie cierpi, i z którego wychodzi nasienie złączenia, dla czego splugawiony bywa.
33 Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.
Także i około niewiasty, chorującej w odłączeniu swem, i każdego cierpiącego płynienie swe, tak mężczyzny, jako i niewiasty, i męża, który leżał z nieczystą.

< Leviticus 15 >