< Leviticus 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Yahvé parla à Moïse et à Aaron, et dit:
2 “Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí ẹ wí fún wọn pé, ‘Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara, ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́.
Parle aux enfants d'Israël, et dis-leur: Si un homme a un écoulement de son corps, il est impur à cause de cet écoulement.
3 Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́:
Voici quelle sera sa souillure dans son écoulement: que son corps coule avec son écoulement, ou que son corps s'arrête à cause de son écoulement, c'est sa souillure.
4 “‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́.
"'Tout lit sur lequel sera couché l'excréteur sera impur, et tout ce sur quoi il s'assiéra sera impur.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Celui qui touchera son lit lavera ses vêtements, se lavera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
6 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Celui qui s'assiéra sur une chose sur laquelle s'est assis l'homme qui a eu des pertes lavera ses vêtements, se lavera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
7 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
"'Celui qui touchera le corps de celui qui a des pertes lavera ses vêtements, se baignera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
8 “‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
"'Si celui qui a l'écoulement crache sur celui qui est pur, il lavera ses vêtements, se baignera dans l'eau, et sera impur jusqu'au soir.
9 “‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́.
"'La selle sur laquelle monte celui qui a l'infection sera impure.
10 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Celui qui touchera ce qui était sous lui sera impur jusqu'au soir. Celui qui porte ces choses lavera ses vêtements, se baignera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
« Si celui qui a l'écoulement touche quelqu'un sans s'être lavé les mains dans l'eau, il lavera ses vêtements, se baignera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
12 “‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.
"'Le vase de terre que touche celui qui a la décharge sera brisé; et tout vase de bois sera rincé à l'eau.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì di mímọ́.
"'Quand celui qui a des pertes sera purifié de ses pertes, il comptera sept jours pour sa purification, il lavera ses vêtements, il baignera son corps dans l'eau courante et il sera pur.
14 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà.
"'Le huitième jour, il prendra deux tourterelles ou deux jeunes pigeons; il se présentera devant l'Éternel, à l'entrée de la tente d'assignation, et les donnera au prêtre.
15 Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.
Le prêtre les offrira, l'une en sacrifice pour le péché, et l'autre en holocauste. Le prêtre fera pour lui l'expiation devant Yahvé, pour qu'il se libère.
16 “‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀, kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
"'Si un homme a une émission de sperme, il lavera toute sa chair dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
17 Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́.
Tout vêtement et toute peau sur lesquels il y a du sperme seront lavés avec de l'eau et seront impurs jusqu'au soir.
18 Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀, kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Si un homme couche avec une femme et qu'il y ait émission de sperme, ils se laveront tous deux dans l'eau et seront impurs jusqu'au soir.
19 “‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀, obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
"'Si une femme a un écoulement, et que cet écoulement soit du sang dans sa chair, elle restera sept jours dans son impureté. Quiconque la touchera sera impur jusqu'au soir.
20 “‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́.
"'Tout ce sur quoi elle se couchera dans son impureté sera impur. Tout ce sur quoi elle s'assiéra sera impur.
21 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Quiconque touchera son lit lavera ses vêtements, se lavera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
22 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Si quelqu'un touche un objet sur lequel elle s'est assise, il lavera ses vêtements, se lavera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
23 Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Si elle est sur le lit ou sur ce sur quoi elle s'est assise, lorsqu'il la touchera, il sera impur jusqu'au soir.
24 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.
"'Si un homme couche avec elle, et que son flux mensuel soit sur lui, il sera impur pendant sept jours; et tout lit sur lequel il couchera sera impur.
25 “‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
"'Si une femme a un écoulement de son sang plusieurs jours en dehors du temps de ses règles, ou si elle a un écoulement au-delà du temps de ses règles, tous les jours de l'écoulement de son impureté seront comme les jours de ses règles. Elle est impure.
26 Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
Tout lit sur lequel elle couchera pendant tous les jours de son écoulement sera pour elle comme le lit de ses règles. Tout ce sur quoi elle s'assiéra sera impur, comme l'impureté de ses règles.
27 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Quiconque touchera ces choses sera impur; il lavera ses vêtements, se baignera dans l'eau et sera impur jusqu'au soir.
28 “‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́.
"'Mais si elle est purifiée de son flux, elle comptera sept jours, et après cela elle sera pure.
29 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Le huitième jour, elle prendra deux tourterelles ou deux jeunes pigeons, et les apportera au prêtre, à l'entrée de la tente d'assignation.
30 Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Le prêtre offrira l'un en sacrifice pour le péché, et l'autre en holocauste; et le prêtre fera pour elle l'expiation devant Yahvé de la souillure qu'elle a commise.
31 “‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́, èyí tí ó wà láàrín wọn.’”
"'Tu sépareras ainsi les enfants d'Israël de leur souillure, afin qu'ils ne meurent pas dans leur souillure lorsqu'ils souilleront mon tabernacle qui est au milieu d'eux'".
32 Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
C'est la loi de celui qui a une décharge et de celui qui a une émission de sperme, de sorte qu'il est impur par cela;
33 Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.
et de celle qui a ses règles, et de l'homme ou de la femme qui a une décharge, et de celui qui couche avec elle qui est impur.

< Leviticus 15 >