< Leviticus 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And he spoke Yahweh to Moses and to Aaron saying.
2 “Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí ẹ wí fún wọn pé, ‘Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara, ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́.
Speak to [the] people of Israel and you will say to them a man a man if he will be discharging from flesh his discharge his [is] unclean it.
3 Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́:
And this it will be uncleanness his by discharge his it has secreted flesh his discharge his or it has been obstructed flesh his from discharge his [is] uncleanness his it.
4 “‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́.
Every bed which he will lie down on it the [one] discharging it will be unclean and every article which he will sit on it it will be unclean.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
And anyone who he will touch bed his he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
6 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And who [-ever] sits on the article which he will sit on it the [one] discharging he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
7 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And who [-ever] touches [the] flesh of the [one] discharging he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
8 “‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And if he will spit the [one] discharging on pure [person] and he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
9 “‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́.
And every saddle which he will ride on it the [one] discharging it will be unclean.
10 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And every [one who] touches all that it will be under him he will be unclean until the evening and who [-ever] carries them he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
And every [one] whom he will touch him the [one] discharging and hands his not he has rinsed with water and he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
12 “‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.
And a vessel of earthenware which he will touch it the [one] discharging it will be broken and every vessel of wood it will be rinsed with water.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì di mímọ́.
And if he will be pure the [one] discharging from discharge his and he will count for himself seven days for purification his and he will wash garments his and he will wash body his with water living and he will be pure.
14 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà.
And on the day eighth he will take for himself two turtle-doves or two young ones of a dove and he will come - before Yahweh to [the] entrance of [the] tent of meeting and he will give them to the priest.
15 Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.
And he will offer them the priest one [bird] a sin offering and the one a burnt offering and he will make atonement on him the priest before Yahweh from discharge his.
16 “‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀, kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
And a man if it will go out from him a laying of seed and he will wash with water all body his and he will be unclean until the evening.
17 Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́.
And every garment and every hide which it will be on it a laying of seed and it will be washed with water and it will be unclean until the evening.
18 Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀, kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And a woman whom he will lie with a man with her a laying of seed and they will wash with water and they will be unclean until the evening.
19 “‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀, obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
And a woman if she will be discharging blood it will be discharge her in flesh her seven days she will be in menstruous impurity her and every [one who] touches her he will be unclean until the evening.
20 “‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́.
And all that she will lie down on it in menstruous impurity her it will be unclean and all that she will sit on it it will be unclean.
21 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And every [one who] touches bed her he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
22 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And every [one who] touches every article which she will sit on it he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
23 Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And if [is] on the bed it or on the article which she [was] sitting on it when touches he it he will be unclean until the evening.
24 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.
And if certainly he will lie with a man with her and it will be menstruous impurity her on him and he will be unclean seven days and every bed which he will lie on it it will be unclean.
25 “‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
And a woman if it will discharge [the] discharge of blood her days many at not [the] time of menstruous impurity her or if she will discharge on menstruous impurity her all [the] days of [the] discharge of uncleanness her like [the] days of menstruous impurity her she will be [is] unclean she.
26 Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
Every bed which she will lie on it all [the] days of discharge her like [the] bed of menstruous impurity her it will be to her and every article which she will sit on it unclean it will be like [the] uncleanness of menstruous impurity her.
27 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
And every [one who] touches them he will be unclean and he will wash garments his and he will wash with water and he will be unclean until the evening.
28 “‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́.
And if she has become pure from discharge her and she will count for herself seven days and after she will be pure.
29 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
And on the day eighth she will take for herself two turtle-doves or two young ones of a dove and she will bring them to the priest to [the] entrance of [the] tent of meeting.
30 Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
And he will offer the priest the one [bird] a sin offering and the one a burnt offering and he will make atonement on her the priest before Yahweh from [the] discharge of uncleanness her.
31 “‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́, èyí tí ó wà láàrín wọn.’”
And you will keep separate [the] people of Israel from uncleanness their and not they will die in uncleanness their because make unclean they dwelling place my which [is] among midst of them.
32 Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
This [is] [the] legal [procedure] of the [one] discharging and [the one] who it will go out from him a laying of seed to be unclean by it.
33 Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.
And the menstruating [woman] in menstruous impurity her and the [one] discharging discharge his for the male and for the female and for a man who he will lie with an unclean [woman].

< Leviticus 15 >