< Leviticus 14 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh also said to Moses/me,
2 “Èyí ni àwọn ìlànà fún ẹni tí ààrùn ẹ̀tẹ̀ bá mú ní àkókò ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, bí a bá mú un tọ àlùfáà wá.
“These are the regulations for anyone who has been healed of a contagious skin disease.
3 Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò ní ẹ̀yìn ibùdó bí ara rẹ̀ bá ti yá kúrò nínú ààrùn ẹ̀tẹ̀ náà.
The person must be brought to a priest. The priest will take him outside the camp [to where that person has been staying], and examine him. If the skin disease has been healed,
4 Kí àlùfáà pàṣẹ pé kí a mú ààyè ẹyẹ mímọ́ méjì, igi kedari, òdòdó àti ẹ̀ka hísópù wá fún ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́.
the priest will say that someone must bring two living birds that are acceptable to Yahweh, along with some cedar wood, some scarlet/red yarn, and some sprigs of (hyssop/a very leafy plant).
5 Kí àlùfáà pàṣẹ pé kí wọn pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sórí omi tí ó mọ́ tó wà nínú ìkòkò amọ̀.
Then the priest will command that one of the birds be killed while [it is being held] over a clay pot containing water from a spring.
6 Lẹ́yìn náà kí ó ri ààyè ẹyẹ pẹ̀lú igi kedari, òdòdó àti ẹ̀ka hísópù bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ tí a ti pa sínú omi náà.
Then the priest will dip the other bird, along with the cedar wood, the scarlet/red yarn and the hyssop, into the blood of the bird that was killed.
7 Ìgbà méje ni kí o wọ́n omi yìí sí ara ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́ kúrò nínú ààrùn ara náà kí ó ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ ní ìta gbangba.
Then he must sprinkle some of the blood on the person who was healed; he must sprinkle it on him seven times. Then he will declare that the person is permitted to be with other people again. And the priest will release the other bird and allow it to fly away.
8 “Ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, fá gbogbo irun rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, lẹ́yìn èyí ó ti di mímọ́. Lẹ́yìn náà ó le wá sínú ibùdó ṣùgbọ́n kí ó wà lẹ́yìn àgọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ méje.
“Then the person who was healed must wash his clothes, shave off all his hair, and bathe. Then he is allowed to return to the camp, but he must stay outside his tent for seven days.
9 Kí ó fá gbogbo irun rẹ̀ ní ọjọ́ keje: irun orí rẹ̀, irùngbọ̀n rẹ̀, irun ìpéǹpéjú rẹ̀, àti gbogbo irun rẹ̀ tókù. Kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì mọ́.
On the seventh day, he must again shave off all his hair, including his beard and his eyebrows. Then he must again wash his clothes and bathe, and then he will be allowed to be with other people again.
10 “Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àgbò aláìlábùkù méjì àti abo ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí wọn kò ní àlébù wá, pẹ̀lú ìdámẹ́wàá nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí à pòpọ̀ mọ́ òróró fún ọrẹ ohun jíjẹ àti òsùwọ̀n lógù òróró kan.
“The next day that person must bring two male lambs and one female lamb that is one year old, all of them with no defects. He must also bring six quarts/liters of fine flour, mixed with olive oil, to be an offering, and (0.6 pint/0.3 liter) of olive oil.
11 Àlùfáà tí ó pè é ní mímọ́, yóò mú ẹni náà tí a ó sọ di mímọ́ àti ọrẹ rẹ̀ wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
The priest who declares that the person’s skin disease is ended must bring that person, and his offerings, to me, Yahweh, at the entrance of the Sacred Tent.
12 “Kí àlùfáà mú ọ̀kan nínú àwọn àgbò àti lógù òróró kí ó sì fi rú ẹbọ ẹ̀bi. Kí ó sì fì wọ́n níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì.
“Then the priest must take one of the male lambs and lift it up, along with the olive oil, in front of me, to be a guilt offering—[an offering for his being guilty for not giving to me the things that he was required to give me].
13 Kí ó pa àgbò náà ní ibi mímọ́ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ sísun. Bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ ẹ̀bi náà jẹ́ ti àlùfáà: ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
Then the priest must slaughter the lamb in the sacred place where the other sacrifices are offered. Like the offering to enable people to be forgiven, this guilt offering is holy, and belongs to the priest.
14 Kí àlùfáà mú nínú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi náà kí ó fi sí etí ọ̀tún ẹni náà tí a ó wẹ̀mọ́, kí ó tún fi sí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti orí àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún rẹ̀.
The priest must take some of the blood of that animal and pour it on the lobe/tip of the right ear and on the thumb of the right hand and on the big toe of the right foot of the one who has been healed of the skin disease.
15 Àlùfáà yóò sì mú díẹ̀ nínú lógù òróró, yóò sì dà á sí àtẹ́lẹwọ́ òsì ara rẹ̀.
Then the priest must take some of the olive oil and pour it in the palm of his own left hand.
16 Yóò sì ti ìka ìfábẹ̀lá ọ̀tún rẹ̀ bọ inú òróró àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀, yóò sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ níwájú Olúwa nígbà méje.
Then he must dip the forefinger of his right hand into the oil in his palm, and sprinkle it in front of me seven times.
17 Àlùfáà yóò mú lára òróró tí ó kù ní àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ yóò fi sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí à ó wẹ̀mọ́, lórí ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi.
Then he must put some of the oil that is still in the palm of his hand on the lobe/tip of the right ear and the thumb of the right hand and on the big toe of the right foot of the person who has been healed of the skin disease. He must put it on top of the blood that he has already put on those places.
18 Àlùfáà yóò fi òróró tí ó kù ní àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ ra orí ẹni tí a ó wẹ̀mọ́, yóò sì ṣe ètùtù fún un níwájú Olúwa.
The remaining oil in his palm must be put on the person’s head, [to indicate that I declare that] the person has been forgiven for having sinned.
19 “Àlùfáà yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, yóò ṣe ètùtù fún ẹni tí a ó wẹ̀ kúrò nínú àìmọ́ rẹ̀, lẹ́yìn náà àlùfáà yóò pa ẹran ọrẹ ẹbọ sísun.
“Then the priest must slaughter one of the other two animals, to show that the one who has been healed of the skin disease has been forgiven for having sinned, and that he has become acceptable to Yahweh. Then the priest will slaughter the animal that will be completely burned [on the altar].
20 Kí àlùfáà kí ó sì rú ẹbọ sísun, àti ẹbọ ohun jíjẹ lórí pẹpẹ, kí àlùfáà kí ó sì ṣe ètùtù fún un, òun yóò sì di mímọ́.
He will also put on the altar the offering of grain, to indicate that the person has been forgiven for having sinned. Then that person will be allowed to be with other people again.
21 “Bí ẹni náà bá jẹ́ tálákà tí kò sì le è kó gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, kí ó mú ọ̀dọ́ àgbò kan bí ẹbọ ẹ̀bi, tí yóò fì, láti ṣe ètùtù fún un, pẹ̀lú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dídára, a pò mọ́ òróró fún ọrẹ ohun jíjẹ òsùwọ̀n lógù òróró
“But if the person who has been healed of a skin disease is poor and cannot afford to bring all those animals, he must take to the priest one male lamb to be lifted up to be an offering for his not giving to me the things that he was required to give me. He must also take two quarts/liters of fine flour mixed with olive oil to be an offering made from grain, (0.6 pint/0.3 liter) of olive oil,
22 àti àdàbà méjì tàbí ẹyẹlé méjì èyí tí agbára rẹ̀ ká, ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun.
and two doves or two young pigeons, one for him to be forgiven for the sins he has committed, and one to be completely burned [on the altar].
23 “Kí ó mú wọn wá ní ọjọ́ kẹjọ fún ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa.
“On that same day, that person must take those things to the priest at the entrance of the Sacred Tent, to offer them to Yahweh.
24 Àlùfáà náà yóò sì mú ọ̀dọ́-àgùntàn ẹbọ ẹ̀bi pẹ̀lú lógù òróró yóò sì fì wọ́n níwájú Olúwa bí ẹbọ fífì.
The priest will take the lamb for the offering for that person not giving to me the things that he was required to give me, along with the olive oil, and lift them up in front of me.
25 Kí ó pa ọ̀dọ́-àgùntàn ẹbọ ẹ̀bi kí ó sì mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Kí ó fi sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ó ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún.
Then the priest will slaughter that lamb [and drain some of the blood in a bowl], and take some of that blood and put it on the lobe/tip of the person’s right ear and on the thumb of his right hand and on the big toe of his right foot.
26 Àlùfáà yóò sì da díẹ̀ lára òróró náà sí àtẹ́lẹwọ́ òsì ara rẹ̀.
Then the priest will pour some of the oil into the palm of his left hand,
27 Yóò sì fi ìka ìfábẹ̀lá ọ̀tún rẹ̀ wọ́n òróró tí ó wà ní àtẹ́lẹwọ́ òsì rẹ̀ nígbà méje níwájú Olúwa.
and with his right forefinger he must sprinkle some of the oil from his palm there in my presence.
28 Àlùfáà yóò sì mú lára òróró ọwọ́ rẹ̀ sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún ní ibi kan náà tí wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi sí.
He must put some of the oil in his palm on the same places where he put the blood.
29 Kí àlùfáà fi ìyókù nínú òróró ọwọ́ rẹ̀ sí orí ẹni náà tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún, láti ṣe ètùtù fún un ní iwájú Olúwa.
He must put the rest of the oil that is in his hand on the head of the person who has been healed of a skin disease, to indicate that I have forgiven him for having sinned.
30 Lẹ́yìn náà kí ó fi àdàbà tàbí ọmọ ẹyẹlé rú ẹbọ níwọ̀n tí agbára rẹ̀ mọ.
Then the priest must sacrifice the doves or the pigeons, whichever that person has brought.
31 Ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ, àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù níwájú Olúwa ní ipò ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́.”
One will be an offering for sin and the other will be completely burned on the altar, along with the offering of grain. By doing that, the priest will declare that the person is no longer guilty for having sinned.
32 Òfin nìyí fún ẹnikẹ́ni tí ó bá ní ààrùn ara tí ó le ran tí kò sì lágbára láti rú ẹbọ tí ó yẹ fún ìwẹ̀nùmọ́ bí a ti fi lélẹ̀.
“Those are the regulations for anyone who has a contagious skin disease and who is poor and cannot afford the usual offerings, in order that he can be with people again.”
33 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé.
Yahweh also said to Aaron and Moses/me,
34 “Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ Kenaani tí mo fi fún yín ní ìní, tí mo sì fi ààrùn ẹ̀tẹ̀ sínú ilé kan ní ilẹ̀ ìní yín.
“I am about to give you Canaan land to belong to your people permanently. When you enter that land, there will be times when I cause/allow mildew to appear inside one of your houses.
35 Kí ẹni tí ó ní ilé náà lọ sọ fún àlùfáà pé, ‘Èmi tí rí ohun tí ó jọ ààrùn ẹ̀tẹ̀ ní ilé mi.’
If that happens, the owner of that house must go to the priest and tell him, ‘There is something in my house that looks like mildew.’
36 Àlùfáà yóò pàṣẹ kí ẹnikẹ́ni tàbí ohunkóhun má ṣe wà nínú ilé náà, kí ó tó lọ yẹ ẹ̀tẹ̀ náà wò, kí ohunkóhun nínú ilé náà má bá à di àìmọ́. Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wọlé lọ láti yẹ ilé náà wò.
“Then the priest will say to him, ‘Take everything out of the house before I enter the house to examine the mildew. If you do not do that, I will declare that everything in the house is contaminated.’
37 Yóò yẹ ààrùn náà wò, bí ààrùn náà bá ti wà lára ògiri ilé náà nípa àmì àwọ̀ ewé tàbí àmì pupa tí ó sì jinlẹ̀, ju ara ògiri lọ.
[After the owner takes everything outside of his house], the priest will go in and inspect the house. If the mildew has caused greenish or reddish spots/depressions on the walls that seem to be deeper than only on the surface of the walls,
38 Àlùfáà yóò jáde kúrò nínú ilé náà, yóò sì ti ìlẹ̀kùn ilé náà pa fún ọjọ́ méje.
the priest will go outside the house and lock it up for seven days.
39 Àlùfáà yóò padà wá yẹ ilé náà wò ní ọjọ́ keje. Bí ààrùn náà bá ti tàn ká ara ògiri.
On the seventh day, he must go into the house and inspect it again. If the mildew on the walls has spread,
40 Àlùfáà yóò pàṣẹ kí a yọ àwọn òkúta tí ààrùn náà ti bàjẹ́ kúrò kí a sì kó wọn dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú.
the priest will tell someone to tear out and throw in the dump outside the town all the stones in the walls that have mildew on them.
41 Yóò sì mú kí wọ́n ha ògiri inú ilé náà yíká. Gbogbo ohun tí wọ́n fi rẹ́ ilé náà tí ó ti ha ni kí wọ́n kó dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú náà.
Then the owner must scrape all the walls inside the house, and everything that is scraped off must be thrown into a dump outside the town.
42 Òkúta mìíràn ni kí wọ́n fi dípò àwọn tí a ti yọ dànù, kí wọ́n sì rẹ́ ilé náà pẹ̀lú àwọn ohun ìrẹ́lé tuntun.
Then the owner must get new/other stones to replace the ones that had mildew on them, and take new clay and plaster [to cover the stones in the walls of] the house.
43 “Bí ààrùn yìí bá tún farahàn lẹ́yìn tí a ti yọ àwọn òkúta wọ̀nyí tí a sì ti ha ilé náà ti a sì tún rẹ́ ẹ.
“If the mildew appears again in the house after that is done,
44 Àlùfáà yóò tún lọ yẹ̀ ẹ́ wò bí ààrùn náà bá tún gbilẹ̀ sí i nínú ilé náà: ẹ̀tẹ̀ apanirun ni èyí, ilé náà jẹ́ aláìmọ́.
the priest must go and examine the house again. If the mildew has spread inside the house, it will be clear that the mildew is the kind that destroys [houses], and no one will be allowed to live in it.
45 Wíwó ni kí a wó o, gbogbo òkúta ilé náà, àwọn igi àti gbogbo ohun tí a fi rẹ́ ẹ ni kí a kó jáde nínú ìlú sí ibi tí a kà sí àìmọ́.
It must be completely torn down—the stones, the timber and the plaster—and all those things must be thrown into a dump outside the town.
46 “Ẹni tí ó bá wọ inú ilé náà lẹ́yìn tí a ti tì í, yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
“Anyone who goes into that house while it is locked up will not be allowed to be with other people until sunset of that day.
47 Ẹni tí ó bá sùn nínú ilé náà tàbí tí ó bá jẹun nínú rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀.
Anyone who sleeps in that house or eats in that house [during that time] must wash his clothes.
48 “Bí àlùfáà bá wá yẹ̀ ẹ́ wò tí ààrùn náà kò gbilẹ̀ mọ́ lẹ́yìn tí a ti rẹ́ ilé náà: kí àlùfáà pe ilé náà ní mímọ́, torí pé ààrùn náà ti lọ.
“But when the priest comes to examine the house after it has been plastered, if the mildew has not spread, he shall declare that people may live in it, because the mildew is gone.
49 Láti sọ ilé yìí di mímọ́. Àlùfáà yóò mú ẹyẹ méjì àti igi kedari òdòdó àti hísópù.
But before people are allowed to live in it, the priest must take two small birds and some cedar wood and some red/scarlet yarn and some hyssop.
50 Yóò sì pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sórí omi tí ó mọ́ nínú ìkòkò amọ̀.
He must kill one of the birds while [holding it] over a clay pot containing water from a spring.
51 Kí ó ri igi kedari, hísópù, òdòdó àti ààyè ẹyẹ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ òkú ẹyẹ àti omi tí ó mọ́ náà kí ó fi wọ́n ilẹ̀ náà lẹ́ẹ̀méje.
Then he must take the cedar wood, the hyssop, the red/scarlet yarn, and the other/living bird, and dip them into the blood of the dead bird, and sprinkle some of that blood on the house seven times.
52 Yóò fi ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ náà, omi tí ó mọ́, ààyè ẹyẹ, igi kedari, hísópù àti òdòdó sọ ilé náà di mímọ́.
By doing all those things he will cause the house to be acceptable to be lived in again.
53 Kí àlùfáà ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ lẹ́yìn ìlú. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún ilé náà. Ilé náà yóò sì mọ́.”
Then he must release the other bird and allow it to fly away. By doing that, he will [finish the ritual for] causing the house to be acceptable for people to live in it again.
54 Àwọn wọ̀nyí ni ìlànà fún èyíkéyìí ààrùn àwọ̀ ara tí ó le è ràn ká, fún làpálàpá,
“Those are the regulations for contagious diseases, for itching sores,
55 àti fún ẹ̀tẹ̀ nínú aṣọ, àti ti ilé,
for mildew [DOU] on clothes or in a house,
56 fún ara wíwú, fún èélá àti ibi ara tí ó ń dán yàtọ̀.
and for swellings, rashes, or bright spots [on sores],
57 Láti mú kí a mọ̀ bóyá nǹkan mọ́ tàbí kò mọ́. Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ààrùn àwọ̀ ara tí ó ń ràn ká àti ẹ̀tẹ̀.
to find out whether a person has a contagious disease or not, and whether people will still be permitted to touch their clothing or their house, or not.”

< Leviticus 14 >