< Leviticus 14 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spoke unto Moses, saying,
2 “Èyí ni àwọn ìlànà fún ẹni tí ààrùn ẹ̀tẹ̀ bá mú ní àkókò ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, bí a bá mú un tọ àlùfáà wá.
This shall be the law of the leper on the day of his being cleansed: He shall be brought unto the priest.
3 Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò ní ẹ̀yìn ibùdó bí ara rẹ̀ bá ti yá kúrò nínú ààrùn ẹ̀tẹ̀ náà.
And the priest shall go forth to without the camp; and if the priest see, and, behold, the plague of leprosy be healed on the leper:
4 Kí àlùfáà pàṣẹ pé kí a mú ààyè ẹyẹ mímọ́ méjì, igi kedari, òdòdó àti ẹ̀ka hísópù wá fún ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́.
Then shall the priest command to take for him that is to be cleansed two healthy, clean birds, and cedar wood, and a string of scarlet yarn, and hyssop.
5 Kí àlùfáà pàṣẹ pé kí wọn pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sórí omi tí ó mọ́ tó wà nínú ìkòkò amọ̀.
And the priest shall command that one of the birds be killed in an earthen vessel over running water.
6 Lẹ́yìn náà kí ó ri ààyè ẹyẹ pẹ̀lú igi kedari, òdòdó àti ẹ̀ka hísópù bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ tí a ti pa sínú omi náà.
As for the living bird, he shall take it, and the cedar wood, and the string of scarlet yarn, and the hyssop, and he shall dip these and the living bird into the blood of the bird that was killed over the running water:
7 Ìgbà méje ni kí o wọ́n omi yìí sí ara ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́ kúrò nínú ààrùn ara náà kí ó ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ ní ìta gbangba.
And he shall sprinkle upon him that is to be cleansed from the leprosy seven times; and when he hath cleansed him, he shall let the living bird fly forth into the open field.
8 “Ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, fá gbogbo irun rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, lẹ́yìn èyí ó ti di mímọ́. Lẹ́yìn náà ó le wá sínú ibùdó ṣùgbọ́n kí ó wà lẹ́yìn àgọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ méje.
And he that is to be cleansed shall wash his clothes, and shave off all his hair, and wash himself in water, and he shall be clean, and after that he may come into the camp; but he shall tarry outside of his tent seven days.
9 Kí ó fá gbogbo irun rẹ̀ ní ọjọ́ keje: irun orí rẹ̀, irùngbọ̀n rẹ̀, irun ìpéǹpéjú rẹ̀, àti gbogbo irun rẹ̀ tókù. Kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì mọ́.
And it shall be on the seventh day, that he shall shave off all his hair, his head, and his beard, and his eyebrows, even all his hair shall he shave off: and he shall wash his clothes, he shall also wash his flesh in water, when he shall be clean.
10 “Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àgbò aláìlábùkù méjì àti abo ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí wọn kò ní àlébù wá, pẹ̀lú ìdámẹ́wàá nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí à pòpọ̀ mọ́ òróró fún ọrẹ ohun jíjẹ àti òsùwọ̀n lógù òróró kan.
And on the eighth day he shall take two sheep without blemish, and one ewe of the first year without blemish, and three-tenth parts of fine flour for a meat-offering, mingled with oil, and one log of oil.
11 Àlùfáà tí ó pè é ní mímọ́, yóò mú ẹni náà tí a ó sọ di mímọ́ àti ọrẹ rẹ̀ wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
And the priest who cleanseth shall cause the man that is to be made clean, and these things, to stand before the Lord, at the door of the tabernacle of the congregation:
12 “Kí àlùfáà mú ọ̀kan nínú àwọn àgbò àti lógù òróró kí ó sì fi rú ẹbọ ẹ̀bi. Kí ó sì fì wọ́n níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì.
And the priest shall take the one sheep, and offer the same for a trespass-offering, with the log of oil; and he shall make with them a waving before the Lord.
13 Kí ó pa àgbò náà ní ibi mímọ́ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ sísun. Bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ ẹ̀bi náà jẹ́ ti àlùfáà: ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
And he shall slay the sheep on the place where the sin-offering and the burnt-offering are killed, in the holy place; for as the sin-offering so doth the trespass-offering belong to the priest: it is most holy.
14 Kí àlùfáà mú nínú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi náà kí ó fi sí etí ọ̀tún ẹni náà tí a ó wẹ̀mọ́, kí ó tún fi sí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti orí àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún rẹ̀.
And the priest shall take some of the blood of the trespass-offering; and the priest shall put it upon the tip of the right ear of him that is to be cleansed, and upon the thumb of his right hand, and upon the great toe of his right foot.
15 Àlùfáà yóò sì mú díẹ̀ nínú lógù òróró, yóò sì dà á sí àtẹ́lẹwọ́ òsì ara rẹ̀.
And the priest shall take some of the log of oil, and pour it into the palm of his own left hand.
16 Yóò sì ti ìka ìfábẹ̀lá ọ̀tún rẹ̀ bọ inú òróró àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀, yóò sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ níwájú Olúwa nígbà méje.
And the priest shall dip his finger of the right hand in the oil that is in his left hand, and he shall sprinkle of the oil with his finger seven times before the Lord.
17 Àlùfáà yóò mú lára òróró tí ó kù ní àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ yóò fi sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí à ó wẹ̀mọ́, lórí ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi.
And of the rest of the oil that is in his hand shall the priest put upon the tip of the right ear of him that is to be cleansed, and upon the thumb of his right hand, and upon the great toe of his right foot, upon the blood of the trespass-offering.
18 Àlùfáà yóò fi òróró tí ó kù ní àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ ra orí ẹni tí a ó wẹ̀mọ́, yóò sì ṣe ètùtù fún un níwájú Olúwa.
And what is left of the oil that is in the priest's hand, he shall put upon the head of him that is to be cleansed: and the priest shall [thus] make an atonement for him before the Lord.
19 “Àlùfáà yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, yóò ṣe ètùtù fún ẹni tí a ó wẹ̀ kúrò nínú àìmọ́ rẹ̀, lẹ́yìn náà àlùfáà yóò pa ẹran ọrẹ ẹbọ sísun.
And the priest shall prepare the sin-offering, and make an atonement for him that is to be cleansed from his uncleanness; and afterward shall he kill the burnt-offering:
20 Kí àlùfáà kí ó sì rú ẹbọ sísun, àti ẹbọ ohun jíjẹ lórí pẹpẹ, kí àlùfáà kí ó sì ṣe ètùtù fún un, òun yóò sì di mímọ́.
And the priest shall offer the burnt-offering and the meat-offering upon the altar; and the priest shall [thus] make an atonement for him, and he shall be clean.
21 “Bí ẹni náà bá jẹ́ tálákà tí kò sì le è kó gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, kí ó mú ọ̀dọ́ àgbò kan bí ẹbọ ẹ̀bi, tí yóò fì, láti ṣe ètùtù fún un, pẹ̀lú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dídára, a pò mọ́ òróró fún ọrẹ ohun jíjẹ òsùwọ̀n lógù òróró
But if he be poor, and his means do not suffice, then shall he take one sheep for a trespass-offering to be waved, to make an atonement for him; and one-tenth part of fine flour mingled with oil for a meat-offering, and a log of oil;
22 àti àdàbà méjì tàbí ẹyẹlé méjì èyí tí agbára rẹ̀ ká, ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun.
And two turtle-doves, or two young pigeons, for which his means suffice; and one shall be a sin-offering, and the other a burnt-offering.
23 “Kí ó mú wọn wá ní ọjọ́ kẹjọ fún ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa.
And he shall bring them on the eighth day of his being cleansed unto the priest, unto the door of the tabernacle of the congregation, before the Lord.
24 Àlùfáà náà yóò sì mú ọ̀dọ́-àgùntàn ẹbọ ẹ̀bi pẹ̀lú lógù òróró yóò sì fì wọ́n níwájú Olúwa bí ẹbọ fífì.
And the priest shall take the sheep of the trespass-offering, and the log of oil; and the priest shall make with them a waving before the Lord.
25 Kí ó pa ọ̀dọ́-àgùntàn ẹbọ ẹ̀bi kí ó sì mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Kí ó fi sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ó ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún.
And he shall kill the sheep of the trespass-offering; and the priest shall take some of the blood of the trespass-offering, and put it upon the tip of the right ear of him that is to be cleansed, and upon the thumb of his right hand, and upon the great toe of his right foot.
26 Àlùfáà yóò sì da díẹ̀ lára òróró náà sí àtẹ́lẹwọ́ òsì ara rẹ̀.
And some of the oil shall the priest pour into the palm of his own left hand:
27 Yóò sì fi ìka ìfábẹ̀lá ọ̀tún rẹ̀ wọ́n òróró tí ó wà ní àtẹ́lẹwọ́ òsì rẹ̀ nígbà méje níwájú Olúwa.
And the priest shall sprinkle with his finger of the right hand some of the oil that is in his left hand, seven times before the Lord;
28 Àlùfáà yóò sì mú lára òróró ọwọ́ rẹ̀ sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún ní ibi kan náà tí wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi sí.
And the priest shall put of the oil that is in his hand upon the tip of the right ear of him that is to be cleansed, and upon the thumb of his right hand, and upon the great toe of his right foot; upon the place of the blood of the trespass-offering;
29 Kí àlùfáà fi ìyókù nínú òróró ọwọ́ rẹ̀ sí orí ẹni náà tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún, láti ṣe ètùtù fún un ní iwájú Olúwa.
And what is left of the oil that is in the priest's hand he shall put upon the head of him that is to be cleansed, to make an atonement for him before the Lord.
30 Lẹ́yìn náà kí ó fi àdàbà tàbí ọmọ ẹyẹlé rú ẹbọ níwọ̀n tí agbára rẹ̀ mọ.
And he shall offer the one of the turtle-doves, or of the young pigeons, from what his means enable him [to bring];
31 Ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ, àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù níwájú Olúwa ní ipò ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́.”
Even what his means enable him, the one for a sin-offering, and the other for a burnt-offering, with the meat-offering: and the priest shall [thus] make an atonement for him that is to be cleansed, before the Lord.
32 Òfin nìyí fún ẹnikẹ́ni tí ó bá ní ààrùn ara tí ó le ran tí kò sì lágbára láti rú ẹbọ tí ó yẹ fún ìwẹ̀nùmọ́ bí a ti fi lélẹ̀.
This is the law of him on whom is the plague of leprosy, whose means are not sufficient when he is cleansed.
33 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé.
And the Lord spoke unto Moses and unto Aaron, saying,
34 “Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ Kenaani tí mo fi fún yín ní ìní, tí mo sì fi ààrùn ẹ̀tẹ̀ sínú ilé kan ní ilẹ̀ ìní yín.
When ye come into the land of Canaan, which I give to you for a possession, and I put the plague of leprosy on a house of the land of your possession:
35 Kí ẹni tí ó ní ilé náà lọ sọ fún àlùfáà pé, ‘Èmi tí rí ohun tí ó jọ ààrùn ẹ̀tẹ̀ ní ilé mi.’
Then shall he that owneth the house come and tell the priest, saying, Something like a leprosy hath shown itself to me in the house.
36 Àlùfáà yóò pàṣẹ kí ẹnikẹ́ni tàbí ohunkóhun má ṣe wà nínú ilé náà, kí ó tó lọ yẹ ẹ̀tẹ̀ náà wò, kí ohunkóhun nínú ilé náà má bá à di àìmọ́. Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wọlé lọ láti yẹ ilé náà wò.
And the priest shall command that they clear out the house, before the priest go into it to see the plague, that all be not made unclean that is in the house: and after this shall the priest go in to see the house.
37 Yóò yẹ ààrùn náà wò, bí ààrùn náà bá ti wà lára ògiri ilé náà nípa àmì àwọ̀ ewé tàbí àmì pupa tí ó sì jinlẹ̀, ju ara ògiri lọ.
And he shall view the plague, and, behold, if the plague be in the walls of the house, in depressions, dark green or dark red, and their appearance be deeper than the wall:
38 Àlùfáà yóò jáde kúrò nínú ilé náà, yóò sì ti ìlẹ̀kùn ilé náà pa fún ọjọ́ méje.
Then shall the priest go out of the house to the door of the house, and lock up the house seven days.
39 Àlùfáà yóò padà wá yẹ ilé náà wò ní ọjọ́ keje. Bí ààrùn náà bá ti tàn ká ara ògiri.
And the priest shall come again on the seventh day; and if he see, that, behold, the plague have spread in the walls of the house:
40 Àlùfáà yóò pàṣẹ kí a yọ àwọn òkúta tí ààrùn náà ti bàjẹ́ kúrò kí a sì kó wọn dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú.
Then shall the priest command that they break out the stones on which the plague is; and they shall cast them forth without the city on an unclean place.
41 Yóò sì mú kí wọ́n ha ògiri inú ilé náà yíká. Gbogbo ohun tí wọ́n fi rẹ́ ilé náà tí ó ti ha ni kí wọ́n kó dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú náà.
And the house he shall cause to be scraped within round about; and they shall pour out the rubbish that they have scraped off without the city on an unclean place.
42 Òkúta mìíràn ni kí wọ́n fi dípò àwọn tí a ti yọ dànù, kí wọ́n sì rẹ́ ilé náà pẹ̀lú àwọn ohun ìrẹ́lé tuntun.
And they shall take other stones, and put them into the place of these stones; and other mortar shall he take, and shall plaster the house.
43 “Bí ààrùn yìí bá tún farahàn lẹ́yìn tí a ti yọ àwọn òkúta wọ̀nyí tí a sì ti ha ilé náà ti a sì tún rẹ́ ẹ.
And if the plague come again, and break out in the house, after he hath taken away the stones, and after the house hath been scraped, and after it hath been plastered:
44 Àlùfáà yóò tún lọ yẹ̀ ẹ́ wò bí ààrùn náà bá tún gbilẹ̀ sí i nínú ilé náà: ẹ̀tẹ̀ apanirun ni èyí, ilé náà jẹ́ aláìmọ́.
Then shall the priest come; and if he see that, behold, the plague have spread in the house, it is a corrosive leprosy in the house; it is unclean.
45 Wíwó ni kí a wó o, gbogbo òkúta ilé náà, àwọn igi àti gbogbo ohun tí a fi rẹ́ ẹ ni kí a kó jáde nínú ìlú sí ibi tí a kà sí àìmọ́.
And he shall break down the house, its stones, and the timbers thereof, and all the mortar of the house; and he shall carry them forth to without the city, unto an unclean place.
46 “Ẹni tí ó bá wọ inú ilé náà lẹ́yìn tí a ti tì í, yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
And he that goeth into the house, all the days that it is locked up, shall be unclean until the evening.
47 Ẹni tí ó bá sùn nínú ilé náà tàbí tí ó bá jẹun nínú rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀.
And he that lieth in the house shall wash his clothes; and he that eateth in the house shall wash his clothes.
48 “Bí àlùfáà bá wá yẹ̀ ẹ́ wò tí ààrùn náà kò gbilẹ̀ mọ́ lẹ́yìn tí a ti rẹ́ ilé náà: kí àlùfáà pe ilé náà ní mímọ́, torí pé ààrùn náà ti lọ.
But if the priest should come in, and see, and, behold, the plague have not spread in the house, after the house was plastered: then shall the priest pronounce the house clean, because the plague is healed.
49 Láti sọ ilé yìí di mímọ́. Àlùfáà yóò mú ẹyẹ méjì àti igi kedari òdòdó àti hísópù.
And he shall take, to atone for the house, two birds, and cedar wood, and a string of scarlet yarn, and hyssop;
50 Yóò sì pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sórí omi tí ó mọ́ nínú ìkòkò amọ̀.
And he shall kill the one bird in an earthen vessel over running water;
51 Kí ó ri igi kedari, hísópù, òdòdó àti ààyè ẹyẹ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ òkú ẹyẹ àti omi tí ó mọ́ náà kí ó fi wọ́n ilẹ̀ náà lẹ́ẹ̀méje.
And he shall take the cedar wood, and the hyssop, and the scarlet yarn, and the living bird, and dip them in the blood of the slain bird, and in the running water, and sprinkle on the house seven times:
52 Yóò fi ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ náà, omi tí ó mọ́, ààyè ẹyẹ, igi kedari, hísópù àti òdòdó sọ ilé náà di mímọ́.
And he shall atone for the house with the blood of the bird, and with the running water, and with the living bird, and with the cedar wood, and with the hyssop, and with the string of scarlet yarn;
53 Kí àlùfáà ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ lẹ́yìn ìlú. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún ilé náà. Ilé náà yóò sì mọ́.”
But he shall let fly forth the living bird out of the city into the open field, and make [thus] an atonement for the house, and it shall be clean.
54 Àwọn wọ̀nyí ni ìlànà fún èyíkéyìí ààrùn àwọ̀ ara tí ó le è ràn ká, fún làpálàpá,
This is the law for all manner of plague of leprosy, and scall,
55 àti fún ẹ̀tẹ̀ nínú aṣọ, àti ti ilé,
And for the leprosy of a garment and of a house,
56 fún ara wíwú, fún èélá àti ibi ara tí ó ń dán yàtọ̀.
And for a swelling, and for a rising, and for a bright spot;
57 Láti mú kí a mọ̀ bóyá nǹkan mọ́ tàbí kò mọ́. Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ààrùn àwọ̀ ara tí ó ń ràn ká àti ẹ̀tẹ̀.
To teach on the day when something is unclean, and on the day when it is clean: this is the law of the leprosy.

< Leviticus 14 >