< Leviticus 12 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
BOEIPA loh Moses te a voek tih,
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé: ‘Obìnrin tí ó bá lóyún tí ó sì bí ọmọkùnrin, yóò wà láìmọ́ fún ọjọ́ méje bí ìgbà tí ó wà ní ipò àìmọ́ lákokò nǹkan oṣù rẹ̀.
Israel ca rhoek te voek lamtah thui pah. Huta he vawn tih capa a cun atah pumom tue vaengah a poeih uh bangla hnin rhih khuiah poeih uh.
3 Ní ọjọ́ kẹjọ ni kí ẹ kọ ọmọ náà ní ilà.
Tedae hnin rhet vaengah camoe kah yahhmui saa te rhet pah saeh.
4 Obìnrin náà yóò sì dúró fún ọjọ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n láti di mímọ́ kúrò nínú ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ kan ohunkóhun tí ó jẹ́ mímọ́ tàbí kí ó lọ sí ibi mímọ́ Olúwa títí di ọjọ́ tí ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ yóò kọjá.
Te phoeiah ciimnah thii dongah khohnin sawmthum hnin thum khosa saeh. A caihcilnah khohnin a cum hlan atah aka cim boeih te ben boel saeh lamtah rhokso lam khaw cet boel saeh.
5 Bí ó bá ṣe obìnrin ni ó bí, fún ọ̀sẹ̀ méjì ni obìnrin náà yóò fi wà ní ipò àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Ó sì gbọdọ̀ dúró ní ọjọ́ mẹ́rìndínláàádọ́rin láti di mímọ́ kúrò nínú ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Tedae huta a cun atah pumom vaengkah bangla yalh khat khuiah poeih uh la om saeh. Te dongah ciimnah thii dongah khohnin sawmrhuk hnin rhuk khosa saeh.
6 “‘Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ fún ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin bá kọjá kí ó mú ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá fún àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé fún ẹbọ sísun àti ọmọ ẹyẹlé tàbí àdàbà kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
A caihcilnah khohnin a cup vaengah atah capa canu kah hmueihhlutnah ham tu kum khat ca neh boirhaem la vahui ca neh vahu mai khaw tingtunnah dap thohka kah khosoih taengla khuen saeh.
7 Ó gbọdọ̀ fi wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa láti ṣe ètùtù fún obìnrin náà lẹ́yìn náà ni yóò di mímọ́ kúrò nínú ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. “‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ìlànà fún obìnrin tí ó bá bí ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin.
Te phoeiah anih ham te BOEIPA mikhmuh ah nawn pah saeh lamtah dawth pah saeh. Te daengah ni anih kah pumthim thii te a caihcil eh. He tah huta tongpa aka cun ham olkhueng ni.
8 Bí kò bá lágbára àti fi àgùntàn ṣe é, ó gbọdọ̀ le mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún un. Òun yóò sì di mímọ́.’”
Tedae a kut loh boiva kangna khaw a hmuh pawt atah vahu phiknit mai khaw, vahui ca phiknit mai khaw hmueihhlutnah ham pakhat, boirhaem ham pakhat te khuen saeh. Te daengah ni anih ham te khosoih loh a dawth pah vetih a caihcil eh?,” a ti nah.

< Leviticus 12 >