< Leviticus 10 >

1 Nadabu àti Abihu tí í ṣe ọmọ Aaroni sì mú àwo tùràrí kọ̀ọ̀kan, wọ́n fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀, wọ́n sì rú iná àjèjì níwájú Olúwa, èyí tó lòdì sí àṣẹ Olúwa.
Nadab et Abihu, fils d'Aaron, prirent chacun leur brasier, y mirent du feu, y déposèrent du parfum, et offrirent devant l'Éternel un feu étranger qu'il ne leur avait pas ordonné.
2 Torí èyí, iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì jó wọn pa, wọ́n sì kú níwájú Olúwa.
Le feu sortit de devant l'Éternel, les dévora, et ils moururent devant l'Éternel.
3 Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Ohun tí Olúwa ń sọ nípa rẹ̀ nìyìí nígbà tó wí pé, “‘Ní àárín àwọn tó súnmọ́ mi, Èmi yóò fi ara mi hàn ní mímọ́ ojú gbogbo ènìyàn Ní a ó ti bu ọlá fún mi.’” Aaroni sì dákẹ́.
Moïse dit alors à Aaron: « C'est ce dont Yahvé a parlé, en disant, Je me montrerai saint pour ceux qui s'approchent de moi, et devant tout le peuple, je serai glorifié. » Aaron se tut.
4 Mose pe Miṣaeli àti Elsafani ọmọ Usieli tí í ṣe arákùnrin Aaroni, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ wá, kí ẹ sì gbé àwọn arákùnrin yín jáde kúrò níwájú ibi mímọ́ lọ sí ẹ̀yìn ibùdó.”
Moïse appela Mischaël et Elzaphan, fils d'Uzziel, oncle d'Aaron, et leur dit: « Approchez, portez hors du camp vos frères qui sont devant le sanctuaire. »
5 Wọ́n sì wá gbé wọn, pẹ̀lú ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọn ní ọrùn wọn lọ sí ẹ̀yìn ibùdó bí Mose ti sọ.
Ils s'approchèrent donc et les transportèrent dans leurs tuniques hors du camp, comme Moïse l'avait dit.
6 Mose sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù, Eleasari àti Itamari pé, “ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ nípa ṣíṣe aláìtọ́jú irun yín tàbí kí ẹ ṣí orí yín sílẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ ya aṣọ, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kùú, Olúwa yóò sì bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn. Ṣùgbọ́n àwọn ẹbí yín, àti gbogbo ilé Israẹli le è ṣọ̀fọ̀ lórí àwọn tí Olúwa fi iná parun.
Moïse dit à Aaron, à Eléazar et à Ithamar, ses fils: « Ne laissez pas tomber les cheveux de vos têtes et ne déchirez pas vos vêtements, afin que vous ne mouriez pas et qu'il ne s'irrite pas contre toute l'assemblée; mais que vos frères, toute la maison d'Israël, se lamentent sur le feu que Yahvé a allumé.
7 Ẹ má ṣe kúrò ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá kúrò níbẹ̀, ẹ ó kù ú, nítorí pé òróró ìtasórí Olúwa wà lórí yín.” Wọ́n sì ṣe bí Mose ti wí.
Tu ne sortiras pas de l'entrée de la tente de la Rencontre, de peur de mourir, car l'huile d'onction de l'Éternel est sur toi. » Ils firent selon la parole de Moïse.
8 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé.
Puis Yahvé dit à Aaron:
9 “Ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀ kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle mìíràn nígbàkígbà tí ẹ bá n lọ inú àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kù ú, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún un yín láti ìrandíran.
« Toi et tes fils, vous ne boirez ni vin ni boisson forte chaque fois que vous entrerez dans la Tente de la Rencontre, sinon vous mourrez. Ceci sera une loi pour toujours, de génération en génération.
10 Ẹ gbọdọ̀ mọ ìyàtọ̀ láàrín mímọ́ àti àìmọ́, láàrín èérí àti àìléèérí.
Tu feras la distinction entre ce qui est saint et ce qui est commun, entre ce qui est impur et ce qui est pur.
11 Ẹ gbọdọ̀ kọ́ àwọn ara Israẹli ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún wọn láti ẹnu Mose.”
Tu enseigneras aux enfants d'Israël toutes les lois que l'Éternel leur a dites par Moïse. »
12 Mose sì sọ fún Aaroni, Eleasari àti Itamari àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù pé, “Ẹ mú ẹbọ ohun jíjẹ tó ṣẹ́kù láti inú ẹbọ àfinásun sí Olúwa, kí ẹ jẹ ẹ́ láìní ìwúkàrà nínú, lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ nítorí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
Moïse parla à Aaron, à Éléazar et à Ithamar, ses fils qui étaient restés: Prenez l'offrande qui reste des sacrifices consumés par le feu devant l'Éternel, et mangez-la sans levure à côté de l'autel, car elle est très sainte.
13 Ẹ jẹ́ ní ibi mímọ́, nítorí pé òun ni ìpín rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nínú ẹbọ tí a finá sun sí Olúwa nítorí pé bẹ́ẹ̀ ni mo ṣe pa á láṣẹ.
Vous la mangerez dans un lieu saint, car c'est votre part et la part de vos fils des sacrifices consumés par le feu devant l'Éternel; c'est ce que je vous ordonne.
14 Ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ le jẹ igẹ̀ ẹran tí a fì níwájú Olúwa àti itan tí wọ́n gbé síwájú Olúwa, kí ẹ jẹ wọ́n ní ibi tí a kà sí mímọ́, èyí ni a ti fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpín yín nínú ẹbọ àlàáfíà àwọn ara Israẹli.
Vous mangerez la poitrine ondulée et la cuisse levée dans un lieu pur, toi, tes fils et tes filles avec toi, car elles sont données comme votre part et la part de vos fils, dans les sacrifices d'actions de grâces des enfants d'Israël.
15 Itan tí wọ́n mú wá àti igẹ̀ ẹran tí ẹ fì ni ẹ gbọdọ̀ mú wá pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ tí a finá sun láti le è fì wọ́n níwájú Olúwa bí ẹbọ fífì. Èyí yóò sì jẹ́ ìpín tìrẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nígbà gbogbo bí Olúwa ṣe pàṣẹ.”
Ils apporteront la cuisse levée et la poitrine agitée, avec les offrandes consumées par le feu de la graisse, pour l'agiter en sacrifice par élévation devant l'Éternel. Ce sera votre part, et celle de vos fils avec vous, comme une part pour toujours, comme Yahvé l'a ordonné. »
16 Nígbà tí Mose wádìí nípa ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tó sì rí i pé wọ́n ti sun ún, ó bínú sí Eleasari àti Itamari, àwọn ọmọ Aaroni yòókù, ó sì béèrè pé,
Moïse s'enquit du bouc du sacrifice pour le péché, et voici qu'il était brûlé. Moïse se mit en colère contre Éléazar et Ithamar, les fils d'Aaron qui restaient, et dit:
17 “Èéṣe tí ẹ kò jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ní agbègbè ibi mímọ́? Ó jẹ́ mímọ́ jùlọ, a fi fún yín láti lè mú ẹ̀ṣẹ̀ ìjọ ènìyàn kúrò nípa fífi ṣe ètùtù fún wọn níwájú Olúwa.
« Pourquoi n'avez-vous pas mangé le sacrifice pour le péché dans le lieu du sanctuaire, puisqu'il est très saint et qu'il vous a été donné de porter l'iniquité de l'assemblée, afin de faire l'expiation pour elle devant Yahvé?
18 Níwọ́n ìgbà tí ẹ kò mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sí Ibi Mímọ́, ẹ̀ bá ti jẹ ewúrẹ́ náà ní agbègbè Ibi Mímọ́ bí mo ṣe pa á láṣẹ.”
Voici, son sang n'a pas été apporté dans l'intérieur du sanctuaire. Vous auriez certainement dû le manger dans le sanctuaire, comme je l'ai ordonné. »
19 Aaroni sì dá Mose lóhùn pé, “Lónìí tí wọ́n rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun wọn níwájú Olúwa ni irú èyí tún ṣẹlẹ̀ sí mi. Ǹjẹ́ inú Olúwa yóò wá dùn bí mo bá jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ lónìí?”
Aaron dit à Moïse: « Voici, ils ont offert aujourd'hui leur sacrifice pour le péché et leur holocauste devant l'Éternel, et il m'est arrivé des choses comme celles-là. Si j'avais mangé aujourd'hui le sacrifice pour le péché, cela aurait-il été agréable aux yeux de Yahvé? ».
20 Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ọkàn rẹ̀ balẹ̀.
Lorsque Moïse entendit cela, cela lui plut.

< Leviticus 10 >