< Leviticus 10 >

1 Nadabu àti Abihu tí í ṣe ọmọ Aaroni sì mú àwo tùràrí kọ̀ọ̀kan, wọ́n fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀, wọ́n sì rú iná àjèjì níwájú Olúwa, èyí tó lòdì sí àṣẹ Olúwa.
Then Aaron’s sons, Nadab and Abihu, took each man his censer and placed therein fire, and put thereon incense, —and brought near before Yahweh strange fire, which he had not commanded them.
2 Torí èyí, iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì jó wọn pa, wọ́n sì kú níwájú Olúwa.
Then came there forth fire from before Yahweh, and consumed them, —and they died before Yahweh.
3 Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Ohun tí Olúwa ń sọ nípa rẹ̀ nìyìí nígbà tó wí pé, “‘Ní àárín àwọn tó súnmọ́ mi, Èmi yóò fi ara mi hàn ní mímọ́ ojú gbogbo ènìyàn Ní a ó ti bu ọlá fún mi.’” Aaroni sì dákẹ́.
Then said Moses unto Aaron—The very thing, that Yahweh spake, saying—In them that draw near to me, must I be hallowed, And before the faces of all the people, must I get myself honour, —And Aaron, was dumb.
4 Mose pe Miṣaeli àti Elsafani ọmọ Usieli tí í ṣe arákùnrin Aaroni, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ wá, kí ẹ sì gbé àwọn arákùnrin yín jáde kúrò níwájú ibi mímọ́ lọ sí ẹ̀yìn ibùdó.”
Then called Moses unto Mishael, and unto Elzaphan, sons of Uzziel, uncle of Aaron, —and said unto them—Draw near bear away your brethren from before the sanctuary, unto the outside of the camp.
5 Wọ́n sì wá gbé wọn, pẹ̀lú ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọn ní ọrùn wọn lọ sí ẹ̀yìn ibùdó bí Mose ti sọ.
So they drew near and bare them away, in their tunics, unto the outside of the camp, —as spake Moses.
6 Mose sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù, Eleasari àti Itamari pé, “ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ nípa ṣíṣe aláìtọ́jú irun yín tàbí kí ẹ ṣí orí yín sílẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ ya aṣọ, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kùú, Olúwa yóò sì bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn. Ṣùgbọ́n àwọn ẹbí yín, àti gbogbo ilé Israẹli le è ṣọ̀fọ̀ lórí àwọn tí Olúwa fi iná parun.
Then said Moses unto Aaron and to Eleazar and to Ithamar, his sons—Your heads, ye may not bare and your garments, ye shall not rend so shall ye not die, neither against all the assembly, will he be wroth, —but let, your brethren the whole house of Israel, bewail the consuming fire wherewith Yahweh hath consumed.
7 Ẹ má ṣe kúrò ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá kúrò níbẹ̀, ẹ ó kù ú, nítorí pé òróró ìtasórí Olúwa wà lórí yín.” Wọ́n sì ṣe bí Mose ti wí.
But, from the entrance of the tent of meeting, shall ye not go forth, lest ye die, for, the anointing oil of Yahweh is upon you. And they did according to the word of Moses.
8 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé.
Then spake Yahweh unto Aaron, saying:
9 “Ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀ kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle mìíràn nígbàkígbà tí ẹ bá n lọ inú àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kù ú, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún un yín láti ìrandíran.
Wine and strong drink, thou mayest not drink, —thou nor thy sons with thee when ye enter into the tent of meeting, so shall ye not die, —an age-abiding statute to your generations;
10 Ẹ gbọdọ̀ mọ ìyàtọ̀ láàrín mímọ́ àti àìmọ́, láàrín èérí àti àìléèérí.
That ye may make a difference, between the sacred and the common, —and between the unclean and the clean;
11 Ẹ gbọdọ̀ kọ́ àwọn ara Israẹli ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún wọn láti ẹnu Mose.”
And may teach the sons of Israel, —all the statutes which Yahweh hath spoken unto them, by the mediation of Moses.
12 Mose sì sọ fún Aaroni, Eleasari àti Itamari àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù pé, “Ẹ mú ẹbọ ohun jíjẹ tó ṣẹ́kù láti inú ẹbọ àfinásun sí Olúwa, kí ẹ jẹ ẹ́ láìní ìwúkàrà nínú, lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ nítorí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
Then spake Moses unto Aaron and unto Eleazar and unto Ithamar his sons that were left, Take ye the meal-offering that is left of the altar-flames of Yahweh, and eat it unleavened beside the altar, —for, most holy, it is;
13 Ẹ jẹ́ ní ibi mímọ́, nítorí pé òun ni ìpín rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nínú ẹbọ tí a finá sun sí Olúwa nítorí pé bẹ́ẹ̀ ni mo ṣe pa á láṣẹ.
therefore shall ye eat it in a holy place, for, thine by statute, and thy sons’ by statute, it is, from among the altar-flames of Yahweh, —for, so, am I commanded.
14 Ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ le jẹ igẹ̀ ẹran tí a fì níwájú Olúwa àti itan tí wọ́n gbé síwájú Olúwa, kí ẹ jẹ wọ́n ní ibi tí a kà sí mímọ́, èyí ni a ti fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpín yín nínú ẹbọ àlàáfíà àwọn ara Israẹli.
And the wave-breast, and the heave-shoulder, shall ye eat in clean place, thou, and thy sons and thy daughters with thee, —for as thine by statute and thy sons’ by statute, have they been given, from among the peace-offerings of the sons of Israel.
15 Itan tí wọ́n mú wá àti igẹ̀ ẹran tí ẹ fì ni ẹ gbọdọ̀ mú wá pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ tí a finá sun láti le è fì wọ́n níwájú Olúwa bí ẹbọ fífì. Èyí yóò sì jẹ́ ìpín tìrẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nígbà gbogbo bí Olúwa ṣe pàṣẹ.”
The heave-shoulder and the wave-breast upon the altar-flames of the fat portions, shall they bring in, to wave as a wave-offering, before Yahweh, —so shall they be thine, and thy sons’ with thee, by an age-abiding statute, As Yahweh hath commanded.
16 Nígbà tí Mose wádìí nípa ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tó sì rí i pé wọ́n ti sun ún, ó bínú sí Eleasari àti Itamari, àwọn ọmọ Aaroni yòókù, ó sì béèrè pé,
Now, as for the sin-bearing goat, Moses diligently sought it but lo! it had been burnt up, —then was he wroth against Eleazar and against Ithamar, the sons of Aaron that were left, saying:
17 “Èéṣe tí ẹ kò jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ní agbègbè ibi mímọ́? Ó jẹ́ mímọ́ jùlọ, a fi fún yín láti lè mú ẹ̀ṣẹ̀ ìjọ ènìyàn kúrò nípa fífi ṣe ètùtù fún wọn níwájú Olúwa.
Wherefore did ye not eat the sin-bearer in the holy place? for most, holy, it is, —and thee same, hath he given you that ye may bear the iniquity of the assembly, to put a propitiatory-covering over them before Yahweh.
18 Níwọ́n ìgbà tí ẹ kò mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sí Ibi Mímọ́, ẹ̀ bá ti jẹ ewúrẹ́ náà ní agbègbè Ibi Mímọ́ bí mo ṣe pa á láṣẹ.”
Lo! the blood thereof had not been taken into the holy place, within, —ye should have, indeed eaten, it, in a holy place, as I commanded.
19 Aaroni sì dá Mose lóhùn pé, “Lónìí tí wọ́n rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun wọn níwájú Olúwa ni irú èyí tún ṣẹlẹ̀ sí mi. Ǹjẹ́ inú Olúwa yóò wá dùn bí mo bá jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ lónìí?”
Then spake Aaron unto Moses—Lo! this very day, when they had brought near their own sin-bearer, and their own ascending-sacrifice, there befell me such things as these, —if, then, I had eaten of the sin-bearer this day, would it have been well-pleasing in the eyes of Yahweh?
20 Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ọkàn rẹ̀ balẹ̀.
And, when Moses heard that, then was it well-pleasing in his eyes.

< Leviticus 10 >