< Leviticus 10 >

1 Nadabu àti Abihu tí í ṣe ọmọ Aaroni sì mú àwo tùràrí kọ̀ọ̀kan, wọ́n fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀, wọ́n sì rú iná àjèjì níwájú Olúwa, èyí tó lòdì sí àṣẹ Olúwa.
Nadab and Abihu, the sons of Aaron [Light-bringer], each took his censer, and put fire in it, and laid incense on it, and offered strange fire before Adonai, which he had not enjoined them.
2 Torí èyí, iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì jó wọn pa, wọ́n sì kú níwájú Olúwa.
Fire came out from before Adonai, and devoured them, and they died before Adonai.
3 Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Ohun tí Olúwa ń sọ nípa rẹ̀ nìyìí nígbà tó wí pé, “‘Ní àárín àwọn tó súnmọ́ mi, Èmi yóò fi ara mi hàn ní mímọ́ ojú gbogbo ènìyàn Ní a ó ti bu ọlá fún mi.’” Aaroni sì dákẹ́.
Then Moses [Drawn out] said to Aaron [Light-bringer], “This is what Adonai spoke of, saying, ‘I will show myself holy to those who come near me, and before all the people I will be glorified.’” Aaron [Light-bringer] held his peace.
4 Mose pe Miṣaeli àti Elsafani ọmọ Usieli tí í ṣe arákùnrin Aaroni, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ wá, kí ẹ sì gbé àwọn arákùnrin yín jáde kúrò níwájú ibi mímọ́ lọ sí ẹ̀yìn ibùdó.”
Moses [Drawn out] called Mishael and Elzaphan, the sons of Uzziel the dod ·uncle· of Aaron [Light-bringer], and said to them, “Draw near, carry your brothers from before the sanctuary out of the camp.”
5 Wọ́n sì wá gbé wọn, pẹ̀lú ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọn ní ọrùn wọn lọ sí ẹ̀yìn ibùdó bí Mose ti sọ.
So they came near, and carried them in their coats out of the camp, as Moses [Drawn out] had said.
6 Mose sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù, Eleasari àti Itamari pé, “ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ nípa ṣíṣe aláìtọ́jú irun yín tàbí kí ẹ ṣí orí yín sílẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ ya aṣọ, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kùú, Olúwa yóò sì bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn. Ṣùgbọ́n àwọn ẹbí yín, àti gbogbo ilé Israẹli le è ṣọ̀fọ̀ lórí àwọn tí Olúwa fi iná parun.
Moses [Drawn out] said to Aaron [Light-bringer], and to Eleazar [Help of God] and to Ithamar, his sons, “Don’t let the hair of your heads go loose, and don’t tear your clothes; so that you don’t die, and so that he not be angry with all the congregation; but let your brothers, the whole house of Israel [God prevails], bewail the burning which Adonai has kindled.
7 Ẹ má ṣe kúrò ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá kúrò níbẹ̀, ẹ ó kù ú, nítorí pé òróró ìtasórí Olúwa wà lórí yín.” Wọ́n sì ṣe bí Mose ti wí.
You shall not go out from the door of the Tent of Meeting, lest you die; for the anointing oil of Adonai is on you.” They did according to the word of Moses [Drawn out].
8 Olúwa sì sọ fún Aaroni pé.
Then Adonai said to Aaron [Light-bringer],
9 “Ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀ kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle mìíràn nígbàkígbà tí ẹ bá n lọ inú àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kù ú, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún un yín láti ìrandíran.
“You and your sons are not to drink wine or strong drink whenever you go into the Tent of Meeting, or you will die. This shall be a regulation forever throughout all your generations.
10 Ẹ gbọdọ̀ mọ ìyàtọ̀ láàrín mímọ́ àti àìmọ́, láàrín èérí àti àìléèérí.
You are to make a distinction between the holy and the common, and between the unclean and the clean.
11 Ẹ gbọdọ̀ kọ́ àwọn ara Israẹli ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún wọn láti ẹnu Mose.”
You are to teach the children of Israel [God prevails] all the statutes which Adonai has spoken to them by Moses [Drawn out].”
12 Mose sì sọ fún Aaroni, Eleasari àti Itamari àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù pé, “Ẹ mú ẹbọ ohun jíjẹ tó ṣẹ́kù láti inú ẹbọ àfinásun sí Olúwa, kí ẹ jẹ ẹ́ láìní ìwúkàrà nínú, lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ nítorí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
Moses [Drawn out] spoke to Aaron [Light-bringer], and to Eleazar [Help of God] and to Ithamar, his sons who were left, “Take the meal offering that remains of the offerings of Adonai made by fire, and eat it without yeast beside the altar; for it is most holy;
13 Ẹ jẹ́ ní ibi mímọ́, nítorí pé òun ni ìpín rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nínú ẹbọ tí a finá sun sí Olúwa nítorí pé bẹ́ẹ̀ ni mo ṣe pa á láṣẹ.
and you shall eat it in a holy place, because it is your chok ·portion·, and your sons’ chok ·portion·, of the offerings of Adonai made by fire: for so I am enjoined.
14 Ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ le jẹ igẹ̀ ẹran tí a fì níwájú Olúwa àti itan tí wọ́n gbé síwájú Olúwa, kí ẹ jẹ wọ́n ní ibi tí a kà sí mímọ́, èyí ni a ti fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpín yín nínú ẹbọ àlàáfíà àwọn ara Israẹli.
The breast that is waved and the thigh that is raised you shall eat in a clean place, you, and your sons, and your daughters with you: for they are given as your chok ·portion·, and your sons’ chok ·portion·, out of the sacrifices of the peace offerings of the children of Israel [God prevails].
15 Itan tí wọ́n mú wá àti igẹ̀ ẹran tí ẹ fì ni ẹ gbọdọ̀ mú wá pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ tí a finá sun láti le è fì wọ́n níwájú Olúwa bí ẹbọ fífì. Èyí yóò sì jẹ́ ìpín tìrẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nígbà gbogbo bí Olúwa ṣe pàṣẹ.”
The thigh that is raised and the breast that is waved they shall bring with the offerings made by fire of the fat, to wave it for a wave offering before Adonai: and it shall be yours, and your sons’ with you, as a chok ·portion· forever; as Adonai has enjoined.”
16 Nígbà tí Mose wádìí nípa ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tó sì rí i pé wọ́n ti sun ún, ó bínú sí Eleasari àti Itamari, àwọn ọmọ Aaroni yòókù, ó sì béèrè pé,
Moses [Drawn out] diligently inquired about the goat of the sin offering, and, behold, it was burned: and he was angry with Eleazar [Help of God] and with Ithamar, the sons of Aaron [Light-bringer] who were left, saying,
17 “Èéṣe tí ẹ kò jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ní agbègbè ibi mímọ́? Ó jẹ́ mímọ́ jùlọ, a fi fún yín láti lè mú ẹ̀ṣẹ̀ ìjọ ènìyàn kúrò nípa fífi ṣe ètùtù fún wọn níwájú Olúwa.
“Why haven’t you eaten the sin offering in the place of the sanctuary, since it is most holy, and he has given it you to bear the iniquity of the congregation, to make atonement for them before Adonai?
18 Níwọ́n ìgbà tí ẹ kò mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sí Ibi Mímọ́, ẹ̀ bá ti jẹ ewúrẹ́ náà ní agbègbè Ibi Mímọ́ bí mo ṣe pa á láṣẹ.”
Behold, its blood was not brought into the inner part of the sanctuary: you certainly should have eaten it in the sanctuary, as I enjoined.”
19 Aaroni sì dá Mose lóhùn pé, “Lónìí tí wọ́n rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun wọn níwájú Olúwa ni irú èyí tún ṣẹlẹ̀ sí mi. Ǹjẹ́ inú Olúwa yóò wá dùn bí mo bá jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ lónìí?”
Aaron [Light-bringer] spoke to Moses [Drawn out], “Behold, today they have offered their sin offering and their burnt offering before Adonai; and such things as these have happened to me. If I had eaten the sin offering today, would it have been pleasing in Adonai’s sight?”
20 Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ọkàn rẹ̀ balẹ̀.
When Moses [Drawn out] sh'ma ·heard obeyed· that, it was pleasing in his sight.

< Leviticus 10 >