< Lamentations 1 >

1 Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan, nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn! Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó wà ní ipò opó, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú ni ó padà di ẹrú.
W biblii siedmdziesięciu tłómaczów, ta księga święta tak się zaczyna. I stało się, gdy Izrael pojmany był, a Jeruzalem spustoszone, że Jeremijasz siedział płacząc, i narzekał narzekaniem takiem nad Jeruzalemem, a rzekł: Ach miasto tak ludne jakoż siedzi samotne! stało się jako wdowa; zacne między narodami, przednie między krainami stało się hołdowne.
2 Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀. Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún. Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀ wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
Ustawicznie w nocy płacze, a łzy jego na jagodach jego; niemasz, ktoby je cieszył ze wszystkich miłośników jego; wszyscy przyjaciele jego przeniewierzyli mu się, stali mu się nieprzyjaciołmi.
3 Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú, Juda lọ sí àjò Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi. Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́ ibi tí kò ti le sá àsálà.
Przeniósł się Juda dla utrapienia i dla wielkiej niewoli; wszakże mieszkając między narodami nie znajduje odpocznienia; wszyscy, którzy je gonią połapali je w cieśni.
4 Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀, nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn. Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro, àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn, àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú, òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
Drogi Syońskie płaczą, że nikt nie przychodzi na święto uroczyste. Wszystkie bramy jego spustoszały, kapłani jego wzdychają, panny jego smutne są, a samo pełne jest gorzkości.
5 Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀, nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀, Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú, ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
Nieprzyjaciele jego są głową, przeciwnikom jego szczęśliwie się powodzi; bo go Pan utrapił dla mnóstwa przestępstwa jego; maluczcy jego poszli w niewolę przed obliczem trapiącego.
6 Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni. Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín tí kò rí ewé tútù jẹ; nínú àárẹ̀ wọ́n sáré níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
A tak odjęta jest od córki Syońskiej wszystka ozdoba jej; książęta jej stały się jako jelenie nie znajdujący paszy, i uchodzą bez siły przed tym, który je goni.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀ tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́. Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá, kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un. Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
Wspomina córka Jeruzalemska we dni utrapienia swego i kwilenia swego na wszystkie uciechy swoje, które miewała ode dni dawnych, gdy pada lud jej od ręki nieprzyjacielskiej, nie mając, ktoby jej ratował; widząc ją nieprzyjaciele naśmiewali się z są batów jej.
8 Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ ó sì ti di aláìmọ́. Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀, nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀; ó kérora fúnra rẹ̀, ó sì lọ kúrò.
Ciężko zgrzeszyła córka Jeruzalemska, przetoż jako nieczysta odłączona jest. Wszyscy, którzy ją w uczciwości mieli, lekce ją sobie ważą, przeto, że widzą nagość jej, a ona wzdycha, i tyłem się obraca.
9 Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀. Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu; olùtùnú kò sì ṣí fún un. “Wo ìpọ́njú mi, Olúwa, nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
Nieczystota jej na podołkach jej, a nie pomniała na koniec swój; przetoż znacznie jest zniżona, nie mając, ktoby ją pocieszył. Wejrzyj, Panie! na utrapienie moje; boć się wyniósł nieprzyjaciel.
10 Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé gbogbo ìní rẹ; o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ— àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀ láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
Rękę swoję wyciągnął nieprzyjaciel na wszystkie kochania jej; bo musi patrzyć na pogan wchodzących do świątnicy jej, o czemeś był przykazał, aby nie wchodzili do zgromadzenia twego.
11 Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ; wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ láti mú wọn wà láààyè. “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó, nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
Wszystek lud jej wzdychając chleba szuka, daje kosztowne rzeczy swoje za pokarm ku posileniu duszy. Wejrzyj, Panie! a obacz; bom znieważona.
12 “Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín? Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá. Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà tí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún mi ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
Nicże was to nie obchodzi? o wszyscy, którzy mimo idziecie drogą! Obaczcie, a oglądajcie, jeźli jest boleść, jako moja boleść, która mi jest zadana, jako mię zasmucił Pan w dzień gniewu zapalczywości swojej.
13 “Ó rán iná láti òkè sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi. Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi, ó sì yí mi padà. Ó ti pa mí lára mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
Z wysokości posłał ogień w kości moje, który je opanował; rozciągnął sieć nogom moim, obrócił mię na wstecz, podał mię na spustoszenie, przez cały dzień żałośną.
14 “Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà; ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀. Wọ́n ti yí ọrùn mi ká Olúwa sì ti dín agbára mi kù. Ó sì ti fi mí lé àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
Związane jest jarzmo nieprawości moich ręką jego, splotły się, wstąpiły na szyję moję; toć poraziło siłę moję; podał mię Pan w ręce nieprzyjaciół, nie mogę powstać.
15 “Olúwa kọ àwọn akọni mi sílẹ̀, ó rán àwọn ológun lòdì sí mi kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run. Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
Pan podeptał wszystkich mocarzy moich w pośród mnie, zwołał przeciwko mnie gromady, aby starł młodzieńców moich, Pan tłoczył jako w prasie pannę, córkę Judzką.
16 “Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún tí omijé sì ń dà lójú mi. Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi, kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà. Àwọn ọmọ mi di aláìní nítorí ọ̀tá ti borí.”
Przetoż ja płaczę; z oczów moich, z oczów moich, mówię, wody cieką, że jest daleko odemnie pocieszyciel, któryby ochłodził duszę moję, synowie moi wytraceni są, przeto, iż wziął górę nieprzyjaciel.
17 Sioni na ọwọ́ jáde, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un. Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un Jerusalẹmu ti di ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
Rozciąga córka Sydońska ręce swoje, nie ma, ktoby ją cieszył; wzbudził Pan na Jakóba zewsząd w około nieprzyjaciół jego; córka Jeruzalemska jest między nimi, niby dla nieczystości oddalona.
18 “Olóòtítọ́ ni Olúwa, ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀. Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn; ẹ wò mí wò ìyà mi. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
Sprawiedliwy jest Pan; bom ustom jego odporna była. Słuchajcie, proszę, wszyscy ludzie, a obaczcie boleść moję; panny moje, i młodzieńcy moi poszli w niewolę.
19 “Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣùgbọ́n wọ́n dà mí. Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi ṣègbé sínú ìlú nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóò mú wọn wà láààyè.
Wołałam na przyjaciół moich, oni mię zdradzili; kapłani moi i starcy moi w mieście zginęli, szukając sobie pokarmu, aby posilili duszę swoję.
20 “Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira! Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi, ìdààmú dé bá ọkàn mi nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi. Ní gbangba ni idà ń parun; ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
Wejrzyż, Panie, bomci utrapiona, wnętrzności moje strwożone są, wywróciło się serce moje we mnie, przeto, żem była bardzo odporna; na dworze miecz osieraca, a w domu nic niemasz jedno śmierć.
21 “Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi. Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi; wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe. Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde, kí wọ́n le dàbí tèmi.
Słysząć, że ja wzdycham, ale niemasz, ktoby mię pocieszył; wszyscy nieprzyjaciele moi słysząc o nieszczęściu mojem weselą się, żeś ty to uczynił, a przywiodłeś dzień przedtem ogłoszony; aleć będą mnie podobni.
22 “Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ; jẹ wọ́n ní yà bí o ṣe jẹ mí ní yà nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ìrora mi pọ̀ ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
Niech przyjdzie wszystka złość ich przed obliczność twoję, a uczyń im, jakoś mnie uczynił dla wszystkich przestępstw moich; bo wielkie są wzdychania moje, a serce moje żałośne.

< Lamentations 1 >