< Lamentations 1 >

1 Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan, nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn! Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó wà ní ipò opó, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú ni ó padà di ẹrú.
Comment la ville est solitaire, qui était plein de gens! Elle est devenue comme une veuve, qui était grand parmi les nations! Elle qui était une princesse parmi les provinces est devenu un esclave!
2 Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀. Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún. Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀ wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
Elle pleure amèrement la nuit. Ses larmes sont sur ses joues. Parmi tous ses amants elle n'a personne pour la réconforter. Tous ses amis l'ont trahie. Ils sont devenus ses ennemis.
3 Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú, Juda lọ sí àjò Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi. Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́ ibi tí kò ti le sá àsálà.
Juda est parti en captivité à cause de l'affliction. et à cause d'une grande servitude. Elle habite parmi les nations. Elle ne trouve pas le repos. Tous ses persécuteurs l'ont rattrapée dans sa détresse.
4 Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀, nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn. Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro, àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn, àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú, òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
Les routes de Sion sont en deuil, parce que personne ne vient à l'assemblée solennelle. Toutes ses portes sont désolées. Ses prêtres soupirent. Ses vierges sont affligées, et elle est elle-même dans l'amertume.
5 Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀, nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀, Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú, ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
Ses adversaires sont devenus la tête. Ses ennemis prospèrent; car Yahvé l'a affligée à cause de la multitude de ses transgressions. Ses jeunes enfants sont partis en captivité devant l'adversaire.
6 Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni. Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín tí kò rí ewé tútù jẹ; nínú àárẹ̀ wọ́n sáré níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
Toute majesté s'est retirée de la fille de Sion. Ses princes sont devenus comme des cerfs qui ne trouvent pas de pâturage. Ils sont partis sans force devant le poursuivant.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀ tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́. Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá, kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un. Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
Jérusalem se souvient, aux jours de son affliction et de ses misères, que toutes ses choses agréables qui étaient des jours d'autrefois; quand son peuple est tombé entre les mains de l'adversaire, et personne ne l'a aidée. Les adversaires l'ont vue. Ils se sont moqués de ses désolations.
8 Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ ó sì ti di aláìmọ́. Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀, nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀; ó kérora fúnra rẹ̀, ó sì lọ kúrò.
Jérusalem a gravement péché. Elle est donc devenue impure. Tous ceux qui l'ont honorée la méprisent, parce qu'ils ont vu sa nudité. Oui, elle soupire et fait demi-tour.
9 Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀. Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu; olùtùnú kò sì ṣí fún un. “Wo ìpọ́njú mi, Olúwa, nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
Sa souillure était dans ses jupes. Elle ne se souvenait pas de sa dernière fin. Elle est donc descendue de façon stupéfiante. Elle n'a pas de doudou. « Vois, Yahvé, mon affliction; car l'ennemi s'est magnifié. »
10 Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé gbogbo ìní rẹ; o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ— àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀ láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
L'adversaire a étendu sa main sur toutes ses choses agréables; car elle a vu que les nations sont entrées dans son sanctuaire, au sujet desquels tu as ordonné qu'ils n'entrent pas dans ton assemblée.
11 Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ; wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ láti mú wọn wà láààyè. “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó, nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
Tout son peuple soupire. Ils cherchent du pain. Ils ont donné leurs choses agréables en guise de nourriture pour rafraîchir leur âme. « Regarde, Yahvé, et vois, car je suis méprisé. »
12 “Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín? Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá. Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà tí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún mi ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
« N'est-ce rien pour vous, vous tous qui passez? Regardez, et voyez s'il y a un chagrin comme le mien, ce qui m'est reproché, dont Yahvé m'a affligé au jour de son ardente colère.
13 “Ó rán iná láti òkè sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi. Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi, ó sì yí mi padà. Ó ti pa mí lára mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
« D'en haut, il a envoyé du feu dans mes os, et elle prévaut contre eux. Il a tendu un filet pour mes pieds. Il m'a fait revenir en arrière. Il m'a rendue désolée et je m'évanouis toute la journée.
14 “Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà; ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀. Wọ́n ti yí ọrùn mi ká Olúwa sì ti dín agbára mi kù. Ó sì ti fi mí lé àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
« Le joug de mes transgressions est lié par sa main. Ils sont liés entre eux. Ils sont montés sur mon cou. Il a fait en sorte que ma force s'effondre. Le Seigneur m'a livré entre leurs mains, contre lequel je ne suis pas capable de tenir.
15 “Olúwa kọ àwọn akọni mi sílẹ̀, ó rán àwọn ológun lòdì sí mi kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run. Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
« L'Éternel a anéanti tous les hommes forts qui étaient en moi. Il a convoqué une assemblée solennelle contre moi pour écraser mes jeunes hommes. Le Seigneur a foulé la fille vierge de Juda comme dans un pressoir.
16 “Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún tí omijé sì ń dà lójú mi. Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi, kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà. Àwọn ọmọ mi di aláìní nítorí ọ̀tá ti borí.”
« C'est pour cela que je pleure. Mon œil, mon œil coule avec de l'eau, car le consolateur qui devrait rafraîchir mon âme est loin de moi. Mes enfants sont désolés, parce que l'ennemi l'a emporté. »
17 Sioni na ọwọ́ jáde, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un. Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un Jerusalẹmu ti di ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
Sion étend ses mains. Il n'y a personne pour la réconforter. que Yahvé a ordonné concernant Jacob, que ceux qui l'entourent soient ses adversaires. Jérusalem est au milieu d'eux comme une chose impure.
18 “Olóòtítọ́ ni Olúwa, ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀. Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn; ẹ wò mí wò ìyà mi. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
« Yahvé est juste, car je me suis rebellé contre son commandement. Veuillez entendre tous les peuples, et voir mon chagrin. Mes vierges et mes jeunes hommes sont partis en captivité.
19 “Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣùgbọ́n wọ́n dà mí. Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi ṣègbé sínú ìlú nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóò mú wọn wà láààyè.
« J'ai appelé mes amants, mais ils m'ont trompé. Mes prêtres et mes anciens ont abandonné l'esprit dans la ville, pendant qu'ils cherchaient de la nourriture pour eux-mêmes afin de rafraîchir leurs âmes.
20 “Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira! Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi, ìdààmú dé bá ọkàn mi nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi. Ní gbangba ni idà ń parun; ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
« Regarde, Yahvé, car je suis dans la détresse. Mon cœur est troublé. Mon cœur se retourne à l'intérieur de moi, car je me suis gravement rebellé. A l'étranger, l'épée endeuille. A la maison, c'est comme la mort.
21 “Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi. Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi; wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe. Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde, kí wọ́n le dàbí tèmi.
« Ils ont entendu que je soupire. Il n'y a personne pour me réconforter. Tous mes ennemis ont entendu parler de mon malheur. Ils sont heureux que vous l'ayez fait. Tu feras venir le jour que tu as annoncé, et ils seront comme moi.
22 “Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ; jẹ wọ́n ní yà bí o ṣe jẹ mí ní yà nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ìrora mi pọ̀ ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
« Quetoute leur méchanceté soit devant toi. Fais-leur comme tu m'as fait pour toutes mes transgressions. Car mes soupirs sont nombreux, et mon cœur est faible.

< Lamentations 1 >