< Lamentations 5 >
1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Згадай, Господи, що́ з нами сталося, — зглянься й побач нашу га́ньбу, —
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
наша спа́дщина діста́лась чужим, доми наші — чужи́нцям!
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Поставали ми си́ротами: нема ба́тька, а ма́тінки наші — неначе ті вдо́ви!
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Свою воду за срі́бло ми п'ємо́, наші дро́ва за гроші оде́ржуємо.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
У поти́лицю нас поганяють, помучені ми, і споко́ю не маємо!
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
До Єгипту й Асирії ру́ку витя́гуємо, — щоб наси́титись хлібом!
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Батьки наші грішили, але їх нема, — а ми двигаємо їхні прови́ни!
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Раби запанува́ли над нами, і немає ніко́го, хто б ви́рятував з їхньої руки.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Нара́жуючи свою душу на меч у пустині, достаємо свій хліб.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Шкіра наша, мов піч, — попали́лась з пекучого голоду,
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Жінок на Сіоні безче́стили, дівчат — по Юдейських містах.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Князі їхньою рукою пові́шені, лиця стари́х не пошано́вані.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Юнаки́ носять камінь млино́вий, а хлопці під ношею дров спотика́ються.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Перестали сиді́ти старші́ в брамі, юнаки́ — свою пісню співати,
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
втіха нашого серця спини́лась, наш та́нець змінивсь на жало́бу.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
Спа́ла корона у нас з голови́, о горе, бо ми прогріши́лись, —
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
тому́ наше серце боля́ще, тому́ наші очі поте́мніли,
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
через го́ру Сіон, що спусто́шена, бро́дять лисиці по ній.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Пробува́єш Ти, Господи, вічно, Твій престо́л з роду в рід:
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Нащо ж на́с забуваєш навік, покидаєш на довгі дні нас?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Приверни́ нас до Себе, о Господи, — і ве́рнемось ми, віднови́ наші дні, як давні́ше було́!
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Хіба́ Ти цілко́м нас відкинув, прогні́вавсь занадто на нас?