< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Señor, por favor, recuerda lo que nos ha pasado. ¡Míranos y date cuenta de cómo hemos sido humillados!
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
La tierra que poseíamos ha sido entregada a extraños, nuestras casas han sido entregadas a extranjeros.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Hemos perdido a nuestros padres y nuestras madres son viudas ahora.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
El agua que bebemos la tenemos que pagar, la leña nos sale cara.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Como animales, nos llevan con arneses al cuello; Estamos agotados, pero no encontramos descanso.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
Nos aliamos con Egipto y Asiria para poder tener mucha comida.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Nuestros antepasados pecaron y se han ido, pero nosotros estamos siendo castigados por sus pecados.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Siervos de nuestro conquistador nos dominan; nadie puede salvarnos de su poder.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Cuando buscamos comida, tomamos nuestras vidas en nuestras manos, a causa de los asaltantes armados en el desierto.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Nuestra piel está caliente como un horno a causa de la fiebre provocada por el hambre.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Violaron a las mujeres en Sión, a las vírgenes en las ciudades de Judá.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
A los príncipes los han colgado de las manos; no respetan a los ancianos.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Los jóvenes son obligados a trabajar en los molinos de mano; los muchachos se tambalean bajo los fardos de leña.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Los ancianos han abandonado sus lugares en la puerta de la ciudad; los jóvenes han dejado de tocar su música.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
Ya no hay alegría para nosotros; nuestro baile se ha convertido en luto.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
La corona ha caído de nuestra cabeza. ¡Qué desastre nos ha sobrevenido por haber pecado!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Por todo esto, estamos enfermos del corazón; por todo esto, podemos apenas mirar;
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
A causa del Monte Sion, que ha sido abandonado, y donde sólo los zorros deambulan.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
¡Pero tú, Señor, vives para siempre! ¡Tú gobiernas por todas las generaciones!
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
¿Por qué nos has olvidado durante tanto tiempo? ¿Por qué nos has abandonado durante tantos años?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Tráenos de regreso a ti, Señor, para que podamos volver a estar contigo. Por favor, restaura nuestras vidas a como era antes.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
¿O es que nos has rechazado por completo? ¿Estás realmente enfadado con nosotros?

< Lamentations 5 >