< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Amintește-ți, DOAMNE, ce a venit peste noi; ia aminte și privește ocara noastră.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Moștenirea noastră s-a întors la străini, casele noastre la necunoscuți.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Noi suntem orfani și fără tată, mamele noastre sunt ca văduvele.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Noi am băut apa noastră pe bani; lemnul nostru ne este vândut nouă.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Gâturile noastre sunt sub persecuție; muncim și nu avem odihnă.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
Am dat mâna cu egiptenii și cu asirienii, ca să ne săturăm cu pâine.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Părinții noștri au păcătuit și nu mai sunt, iar noi am purtat nelegiuirile lor.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Servitori au condus peste noi, nu este nimeni care să ne elibereze din mâna lor.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Ne câștigăm pâinea cu riscul vieților noastre din cauza sabiei pustiei.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Pielea noastră era neagră ca un cuptor din cauza foametei teribile.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Ei au necinstit femeile în Sion și pe fecioarele din cetățile lui Iuda.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Prinți sunt spânzurați prin mâna lor; fețele bătrânilor nu au fost onorate.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Ei au luat pe tineri să macine și copiii au căzut sub lemne.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Bătrânii au încetat [să mai fie] la poartă, tinerii la muzica lor.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
Bucuria inimii noastre a încetat; dansul nostru este întors în jale.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
Coroana a căzut de pe capul nostru; vai de noi, pentru că am păcătuit!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Fiindcă inima noastră [este] leșinată; pentru aceste lucruri ochii noștri sunt întunecați.
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
Din cauza muntelui Sionului, care este pustiit, vulpile se plimbă pe el.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Tu, DOAMNE, rămâi pentru totdeauna; tronul tău din generație în generație.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Pentru ce ne uiți pentru totdeauna și ne părăsești atât de mult timp?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Întoarce-ne la tine, DOAMNE și ne vom întoarce; înnoiește-ne zilele ca în vechime.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Dar tu ne-ai respins pe deplin, te-ai înfuriat tare împotriva noastră.

< Lamentations 5 >