< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Lembre-se, Yahweh, do que nos aconteceu. Veja, e veja nossa reprovação.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Our a herança foi entregue a estranhos, nossas casas para alienígenas.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
We são órfãos e sem pai. Nossas mães são como viúvas.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
We deve pagar pela água para beber. Nossa madeira é vendida para nós.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Nossos perseguidores estão em nossos pescoços. Estamos cansados, e não temos descanso.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
We deram nossas mãos aos egípcios, e aos assírios, para ficar satisfeitos com o pão.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Nossos pais pecaram, e não são mais. Nós suportamos suas iniqüidades.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Os serventes dominam sobre nós. Não há ninguém para nos livrar de suas mãos.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Nós recebemos nosso pão em perigo de vida, por causa da espada no deserto.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Nossa pele é preta como um forno, por causa do calor abrasador da fome.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
They arrebatou as mulheres em Zion, as virgens nas cidades de Judá.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Os príncipes foram pendurados pelas mãos. Os rostos dos mais velhos não foram homenageados.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Os jovens carregam pedras de moinho. As crianças tropeçaram sob cargas de madeira.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Os anciãos deixaram o portal, e os jovens de sua música.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
A alegria de nosso coração cessou. Nossa dança se transforma em luto.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
A coroa caiu de nossa cabeça. Ai de nós, pois pecamos!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Para isso, nosso coração está fraco. Para estas coisas, nossos olhos estão baixos:
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
para a montanha de Sião, que está desolada. As raposas caminham sobre ela.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Você, Yahweh, permanece para sempre. Seu trono é de geração em geração.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Por que você nos esquece para sempre? e nos abandona por tanto tempo?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Volte-nos para si mesmo, Yahweh, e nós seremos voltados. Renovar nossos dias de antigamente.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Mas você nos rejeitou totalmente. Você está muito zangado contra nós.

< Lamentations 5 >