< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Lembra-te, SENHOR, do que tem nos acontecido; presta atenção e olha nossa humilhação.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Nossa herança passou a ser de estrangeiros, nossas casas de forasteiros.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Órfãos somos sem pai, nossas mães são como viúvas.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Bebemos nossa água por dinheiro; nossa lenha temos que pagar.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Perseguição sofremos sobre nossos pescoços; estamos cansados, mas não temos descanso.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
Nós nos rendemos aos egípcios e aos assírios para nos saciarmos de pão.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Nossos pais pecaram, e não existem mais; porém nós levamos seus castigos.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Servos passaram a nos dominar; ninguém há que [nos] livre de suas mãos.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Com risco de vida trazemos nosso pão, por causa da espada do deserto.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Nossa pele se tornou negra como um forno, por causa do ardor da fome.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Abusaram das mulheres em Sião, das virgens nas cidades de Judá.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Os príncipes foram enforcados por sua mãos; não respeitaram as faces dos velhos.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Levaram os rapazes para moer, e os moços caíram debaixo da lenha [que carregavam].
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Os anciãos deixaram de [se sentarem] junto as portas, os rapazes de suas canções.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
Acabou a alegria de nosso coração; nossa dança se tornou em luto.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
Caiu a coroa de nossa cabeça; ai agora de nós, porque pecamos.
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Por isso nosso coração ficou fraco, por isso nossos olhos escureceram;
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
Por causa do monte de Sião, que está desolado; raposas andam nele.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Tu, SENHOR, permanecerás para sempre; [e] teu trono de geração após geração.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Por que te esquecerias de nós para sempre e nos abandonarias por tanto tempo?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Converte-nos, SENHOR, a ti, e seremos convertidos; renova o nossos dias como antes;
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
A não ser que tenhas nos rejeitado totalmente, e estejas enfurecido contra nós ao extremo.

< Lamentations 5 >