< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Ricordati, Eterno, di quello che ci è avvenuto! Guarda e vedi il nostro obbrobrio!
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
La nostra eredità è passata a degli stranieri, le nostre case, a degli estranei.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Noi siam diventati orfani, senza padre, le nostre madri son come vedove.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Noi beviamo la nostr’acqua a prezzo di danaro, le nostre legna ci vengono a pagamento.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Col collo carico noi siamo inseguiti, siamo spossati, non abbiamo requie.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
Abbiam teso la mano verso l’Egitto e verso l’Assiria, per saziarci di pane.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
I nostri padri hanno peccato, e non sono più; e noi portiamo la pena delle loro iniquità.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Degli schiavi dominano su noi, e non v’è chi ci liberi dalle loro mani.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Noi raccogliamo il nostro pane col rischio della nostra vita, affrontando la spada del deserto.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
La nostra pelle brucia come un forno, per l’arsura della fame.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Essi hanno disonorato le donne in Sion, le vergini nelle città di Giuda.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
I capi sono stati impiccati dalle loro mani, la persona de’ vecchi non è stata rispettata.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
I giovani han portato le macine, i giovanetti han vacillato sotto il carico delle legna.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
I vecchi hanno abbandonato la porta, i giovani la musica dei loro strumenti.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
La gioia de’ nostri cuori è cessata, le nostre danze son mutate in lutto.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
La corona ci è caduta dal capo; guai a noi, poiché abbiamo peccato!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Per questo langue il nostro cuore, per questo s’oscuran gli occhi nostri:
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
perché il monte di Sion è desolato, e vi passeggian le volpi.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Ma tu, o Eterno, regni in perpetuo; il tuo trono sussiste d’età in età.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Perché ci dimenticheresti tu in perpetuo, e ci abbandoneresti per un lungo tempo?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Facci tornare a te, o Eterno, e noi torneremo! Ridonaci de’ giorni come quelli d’un tempo!
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Ché, ora, tu ci hai veramente reietti, e ti sei grandemente adirato contro di noi!

< Lamentations 5 >