< Lamentations 5 >
1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Ricordati, Signore, di quanto ci è accaduto, guarda e considera il nostro obbrobrio.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
La nostra eredità è passata a stranieri, le nostre case a estranei.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Orfani siam diventati, senza padre; le nostre madri come vedove.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
L'acqua nostra beviamo per denaro, la nostra legna si acquista a pagamento.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Con un giogo sul collo siamo perseguitati siamo sfiniti, non c'è per noi riposo.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
All'Egitto abbiamo teso la mano, all'Assiria per saziarci di pane.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
I nostri padri peccarono e non sono più, noi portiamo la pena delle loro iniquità.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Schiavi comandano su di noi, non c'è chi ci liberi dalle loro mani.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
A rischio della nostra vita ci procuriamo il pane davanti alla spada nel deserto.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
La nostra pelle si è fatta bruciante come un forno a causa degli ardori della fame.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Han disonorato le donne in Sion, le vergini nelle città di Giuda.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
I capi sono stati impiccati dalle loro mani, i volti degli anziani non sono stati rispettati.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
I giovani han girato la mola; i ragazzi son caduti sotto il peso della legna.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Gli anziani hanno disertato la porta, i giovani i loro strumenti a corda.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
La gioia si è spenta nei nostri cuori, si è mutata in lutto la nostra danza.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
E' caduta la corona dalla nostra testa; guai a noi, perché abbiamo peccato!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Per questo è diventato mesto il nostro cuore, per tali cose si sono annebbiati i nostri occhi:
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
perché il monte di Sion è desolato; le volpi vi scorrazzano.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Ma tu, Signore, rimani per sempre, il tuo trono di generazione in generazione.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Perché ci vuoi dimenticare per sempre? Ci vuoi abbandonare per lunghi giorni?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Facci ritornare a te, Signore, e noi ritorneremo; rinnova i nostri giorni come in antico,
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
poiché non ci hai rigettati per sempre, nè senza limite sei sdegnato contro di noi.