< Lamentations 5 >
1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Emlékezzél meg Uram, mi esett meg rajtunk; tekintsd meg és lásd meg gyalázatunkat!
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
A mi örökségünk idegenekre szállt; házaink a jövevényekéi.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Apátlan árvák lettünk; anyáink, mint az özvegyek.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Vizünket pénzért iszszuk, tűzifánkat áron kapjuk.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Nyakunknál fogva hajtatunk; elfáradtunk, nincsen nyugtunk.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
Égyiptomnak adtunk kezet, az assziroknak, hogy jóllakjunk kenyérrel.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Apáink vétkeztek; nincsenek; mi hordozzuk vétkeiket.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Szolgák uralkodnak rajtunk; nincs a ki megszabadítson kezökből.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Életünk veszélyeztetésével szerezzük kenyerünket a pusztában levő fegyver miatt.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Bőrünk, mint a kemencze, megfeketedett az éhség lázától.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Az asszonyokat meggyalázták Sionban, a szűzeket Júda városaiban.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
A fejedelmeket kezökkel akasztották fel; a vének orczáit nem becsülik.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Az ifjak a kézi malmot hordozzák, és a gyermekek a fahordásban botlanak el.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
A vének eltüntek a kapuból, megszüntek az ifjak énekelni.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
Oda van a mi szívünk öröme, gyászra fordult a mi körtánczunk.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
Elesett a mi fejünknek koronája, jaj most nékünk mert vétkeztünk!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Ezért lett beteg a mi szívünk, ezekért homályosodtak meg a mi szemeink;
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
A Sion hegyéért, hogy elpusztult; rókák futkosnak azon!
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Te Uram örökké megmaradsz; a te királyi széked nemzedékről nemzedékre!
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Miért feledkezel el örökre mi rólunk? miért hagysz el minket hosszú időre?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Téríts vissza Uram magadhoz és visszatérünk; újítsd meg a mi napjainkat, mint régen.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Mert bizony-bizony megvetettél minket; megharagudtál ránk felettébb!