< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
זכר יהוה מה היה לנו הביט וראה את חרפתנו׃
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
נחלתנו נהפכה לזרים בתינו לנכרים׃
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
יתומים היינו אין אב אמתינו כאלמנות׃
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
מימינו בכסף שתינו עצינו במחיר יבאו׃
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
על צוארנו נרדפנו יגענו לא הונח לנו׃
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
מצרים נתנו יד אשור לשבע לחם׃
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
אבתינו חטאו אינם אנחנו עונתיהם סבלנו׃
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
עבדים משלו בנו פרק אין מידם׃
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
בנפשנו נביא לחמנו מפני חרב המדבר׃
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
עורנו כתנור נכמרו מפני זלעפות רעב׃
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
נשים בציון ענו בתלת בערי יהודה׃
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
שרים בידם נתלו פני זקנים לא נהדרו׃
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
בחורים טחון נשאו ונערים בעץ כשלו׃
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
זקנים משער שבתו בחורים מנגינתם׃
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
שבת משוש לבנו נהפך לאבל מחלנו׃
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
נפלה עטרת ראשנו אוי נא לנו כי חטאנו׃
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
על זה היה דוה לבנו על אלה חשכו עינינו׃
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
על הר ציון ששמם שועלים הלכו בו׃
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
אתה יהוה לעולם תשב כסאך לדר ודור׃
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
למה לנצח תשכחנו תעזבנו לארך ימים׃
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
השיבנו יהוה אליך ונשוב חדש ימינו כקדם׃
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
כי אם מאס מאסתנו קצפת עלינו עד מאד׃

< Lamentations 5 >