< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Gedenke, HERR, wie es uns geht; schaue und siehe an unsre Schmach!
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Unser Erbe ist den Fremden zuteil geworden und unsre Häuser den Ausländern.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Wir sind Waisen und haben keinen Vater; unsre Mütter sind Witwen.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Unser Wasser müssen wir um Geld trinken; unser Holz muß man bezahlt bringen lassen.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Man treibt uns über Hals; und wenn wir schon müde sind, läßt man uns doch keine Ruhe.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
Wir haben uns müssen Ägypten und Assur ergeben, auf daß wir Brot satt zu essen haben.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Unsre Väter haben gesündigt und sind nicht mehr vorhanden, und wir müssen ihre Missetaten entgelten.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Knechte herrschen über uns, und ist niemand, der uns von ihrer Hand errette.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Wir müssen unser Brot mit Gefahr unsers Lebens holen vor dem Schwert in der Wüste.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Unsre Haut ist verbrannt wie in einem Ofen vor dem greulichen Hunger.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Sie haben die Weiber zu Zion geschwächt und die Jungfrauen in den Städten Juda's.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Die Fürsten sind von ihnen gehenkt, und die Person der Alten hat man nicht geehrt.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Die Jünglinge haben Mühlsteine müssen tragen und die Knaben über dem Holztragen straucheln.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Es sitzen die Alten nicht mehr unter dem Tor, und die Jünglinge treiben kein Saitenspiel mehr.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
Unsers Herzens Freude hat ein Ende; unser Reigen ist in Wehklagen verkehrt.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
Die Krone unsers Hauptes ist abgefallen. O weh, daß wir so gesündigt haben!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Darum ist auch unser Herz betrübt, und unsre Augen sind finster geworden
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
um des Berges Zion willen, daß er so wüst liegt, daß die Füchse darüber laufen.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Aber du, HERR, der du ewiglich bleibst und dein Thron für und für,
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
warum willst du unser so gar vergessen und uns lebenslang so gar verlassen?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Bringe uns, HERR, wieder zu dir, daß wir wieder heimkommen; erneuere unsre Tage wie vor alters!
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Denn du hast uns verworfen und bist allzusehr über uns erzürnt.

< Lamentations 5 >