< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Remember, LORD, what has come on us. Look, and see our disgrace.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Our inheritance is turned over to strangers, our houses to foreigners.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
We are orphans and fatherless. Our mothers are like widows.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
We have to pay for a drink of water; our wood is sold to us.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Our pursuers are on our necks; we are weary, and have no rest.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
We have submitted to the Egyptians and to the Assyrians, to get enough bread.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Our fathers sinned, and are no more; but we have borne their iniquities.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Servants rule over us: There is none to deliver us out of their hand.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
We get our bread at the peril of our lives, because of the sword in the wilderness.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Our skin is hot like an oven, because of the burning heat of famine.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
They raped the women in Zion, the virgins in the cities of Judah.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Princes were hung by their hands; elders were shown no respect.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
The young men grind at the mill; the boys stagger under loads of wood.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
The elders have gone from the gate, the young men from their music.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
The joy of our heart has ceased; our dancing is turned into mourning.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
The crown is fallen from our head; woe to us, for we have sinned.
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
For this our heart is faint; for these things our eyes grow dim.
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
For the mountain of Zion, which is desolate; the foxes walk on it.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
But you, LORD, abide forever; your throne is from generation to generation.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Why do you keep on forgetting us? Why do you forsake us so long?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Restore us to you, LORD, and we shall be restored; renew our days as in former times,
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
unless you have completely rejected us and are angry with us beyond measure.

< Lamentations 5 >