< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Remember, O YHWH, what has befallen us, Look attentively, and see our reproach.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Our inheritance has been turned to strangers, Our houses to foreigners.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Orphans we have been—without a father, our mothers [are] as widows.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
We have drunk our water for money, Our wood comes for a price.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
For our neck we have been pursued, We have labored—there has been no rest for us.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
[To] Egypt we have given a hand, [To] Asshur, to be satisfied with bread.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Our fathers have sinned—they are not, We have borne their iniquities.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Servants have ruled over us, There is no deliverer from their hand.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
With our lives we bring in our bread, Because of the sword of the wilderness.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Our skin as an oven has been burning, Because of the raging of the famine.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Wives in Zion they have humbled, Virgins—in cities of Judah.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Princes have been hanged by their hand, Elderly faces have not been honored.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
They have taken young men to grind, And youths have stumbled with wood.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Elderly have ceased from the gate, Young men from their song.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
The joy of our heart has ceased, Our dancing has been turned to mourning.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
The crown has fallen [from] our head, Woe [is] now to us, for we have sinned.
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Our heart has been sick for this, Our eyes have been dim for these.
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
For the Mount of Zion—that is desolate, Foxes have gone up on it.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
You, O YHWH, remain for all time, Your throne to generation and generation.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Why do You forget us forever? You forsake us for [the] length of [our] days!
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Turn us back, O YHWH, to You, And we turn back, renew our days as of old.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
For have You utterly rejected us? You have been angry against us—exceedingly?

< Lamentations 5 >