< Lamentations 5 >
1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Remember, O Jehovah, what is come upon us; consider, and see our reproach.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Our inheritance is turned to strangers, our houses to aliens.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
We are orphans and fatherless, our mothers are as widows.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Our water have we to drink for money, our wood cometh unto us for a price.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Our pursuers are on our necks: we are weary, we have no rest.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
We have given the hand to Egypt, [and] to Asshur, to be satisfied with bread.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Our fathers have sinned, [and] they are not; and we bear their iniquities.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Bondmen rule over us: there is no deliverer out of their hand.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
We have to get our bread at the risk of our lives, because of the sword of the wilderness.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Our skin gloweth like an oven, because of the burning heat of the famine.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
They have ravished the women in Zion, the maids in the cities of Judah.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Princes were hanged up by their hand; the faces of elders were not honoured.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
The young men have borne the mill, and the youths have stumbled under the wood.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
The elders have ceased from the gate, the young men from their music.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
The joy of our heart hath ceased; our dance is turned into mourning.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
The crown is fallen from our head: woe unto us, for we have sinned!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
For this our heart is faint; for these things our eyes have grown dim,
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
Because of the mountain of Zion, which is desolate: foxes walk over it.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Thou, Jehovah, dwellest for ever; thy throne is from generation to generation.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Wherefore dost thou forget us for ever, dost thou forsake us so long time?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Turn thou us unto thee, Jehovah, and we shall be turned; renew our days as of old.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Or is it that thou hast utterly rejected us? Wouldest thou be exceeding wroth against us?