< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Keep in mind, O Lord, what has come to us: take note and see our shame.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Our heritage is given up to men of strange lands, our houses to those who are not our countrymen.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
We are children without fathers, our mothers are like widows.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
We give money for a drink of water, we get our wood for a price.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Our attackers are on our necks: overcome with weariness, we have no rest.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
We have given our hands to the Egyptians and to the Assyrians so that we might have enough bread.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Our fathers were sinners and are dead; and the weight of their evil-doing is on us.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Servants are ruling over us, and there is no one to make us free from their hands.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
We put our lives in danger to get our bread, because of the sword of the waste land.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Our skin is heated like an oven because of our burning heat from need of food.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
They took by force the women in Zion, the virgins in the towns of Judah.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Their hands put princes to death by hanging: the faces of old men were not honoured.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
The young men were crushing the grain, and the boys were falling under the wood.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
The old men are no longer seated in the doorway, and the music of the young men has come to an end.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
The joy of our hearts is ended; our dancing is changed into sorrow.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
The crown has been taken from our head: sorrow is ours, for we are sinners.
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
Because of this our hearts are feeble; for these things our eyes are dark;
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
Because of the mountain of Zion which is a waste; jackals go over it.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
You, O Lord, are seated as King for ever; the seat of your power is eternal.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Why have we gone from your memory for ever? why have you been turned away from us for so long?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Make us come back to you, O Lord, and let us be turned; make our days new again as in the past.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
But you have quite given us up; you are full of wrath against us.

< Lamentations 5 >