< Lamentations 4 >

1 Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù, wúrà dídára di àìdán! Òkúta ibi mímọ́ wá túká sí oríta gbogbo òpópó.
NANI ka mae wale ana o ke gula! A me ke ano e ana o ke gula maikai! Ua hooleiia na pohaku o kahi hoano ma ke poo o na alanui a pau.
2 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye, tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
O na keiki nani o Ziona i kau pu ia me ke gula maikai, Nani ko lakou manao like ia me na ipu lepo, Ka hana a na lima o ka potera!
3 Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn bí ògòǹgò ní aginjù.
Unuhi ae no na ia nui i ka omaka waiu, A hanai waiu aku i ka lakou poe keiki: Aka, ua lokoino ke kaikamahine a ko'u poe kanaka, E like me na Iana o ka waonahele.
4 Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́ lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn; àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
Ua pipili ke alelo o ke keiki ai waiu i ke aluna o ka waha, no ka makewai; Nonoi aku na keiki i ka berena, Aohe mea nana e haawi aku na lakou.
5 Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára di òtòṣì ní òpópó. Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀ ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
O ka poe i ai i ka ai maikai, Ua wailana lakou ma na alanui, O ka poe hoi i aahuia i ka lole ula, Ua apo iho lakou i na puu lepo.
6 Ìjìyà àwọn ènìyàn mi tóbi ju ti Sodomu lọ, tí a sí ní ipò ní òjijì láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
Ua hooiia'ku ka hewa o ke kaikamahine a ko'u poe kanaka, Mamua o ka hewa o ko Sodoma, Ka mea i hookahuliia ma ke amo aua o ka maka, Aohe lima ikaika maluna ona,
7 Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì, wọ́n sì funfun ju wàrà lọ wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa, ìrísí wọn dàbí safire.
Oi aku ka maemae o kona poe laa, mamua o ko ka hau, Oi aku ko lakou keokeo mamua o ka waiu, Oi aku ka ula o ke kino, i ko na pohaku ula, A like ko lakou helehelena me ko ka sapeiro.
8 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú; wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó. Ara wọn hun mọ́ egungun; ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
Ua oi aku ka eleelo o ko lakou helehelena i ko ka pouli, Aole lakou i ikeia ma na alanui; Ua pipili ko lakou ili i ko lakou mau iwi, Ua maloo, ua like hoi me ka laau.
9 Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn ju àwọn tí ìyàn pa; tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
Ua oi ka pomaikai o ka poe i make i ka pahikaua, mamua o ko ka poe i make i ka pololi: Hokii ae la keia poe, ua houia no ka hua ole o ka mahinaai.
10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ tí ó di oúnjẹ fún wọn nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
O na lima o na wahine aloha, ua hoolapalapa lakou i ka lakou mau keiki iho; O lakou no ka lakou ai i ka make ana o ke kaikamahine a ko'u poe kanaka.
11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀; ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde. Ó da iná ní Sioni tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
Ua hooko mai o Iehova i kona huhu, Ua ninini mai oia i kona inaina nui; Ua hoa oia i ke ahi maloko o Ziona, A ua ai ia i kana mau kumu.
12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́, tàbí àwọn ènìyàn ayé, wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ odi ìlú Jerusalẹmu.
Aole i hiki i na'lii o ka honua, a me ka poe a pau e noho la ma ke ao nei, ke manao, E komo mai ana ka enemi, a me ka mea huhu iloko o na pukapa o Ierusalema.
13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà, tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
No ka hewa o kona mau kaula, ka hala hoi o kona mau kahuna, Ka poe i hookahe i ke koko o ka poe pono iwaenakonu ona,
14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó bí ọkùnrin tí ó fọ́jú. Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
Kuewa makapo aku lakou ma na alanui, Ua hoohaumia ia lakou iho i ko koko, Nolaila, aole hiki ke hoopa aku i ko lakou aahu.
15 “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn. “Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!” Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé, “Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
Kahea mai la na kanaka ia lakou, E hele aku, ua haumia; E hele aku, e hele aku, mai hoopa aku; Ia lakou i holo ai, a kuewa aku, i ae la lakou iwaena o ko na aina e, Aole lakou e noho hou.
16 Olúwa ti tú wọn ká fúnra rẹ̀; kò sí bojútó wọn mọ́. Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́, àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
Na ka maka o Iehova i hoopuehu lakou; Aole ia e manao hou mai ia lakou; Aole lakou i manao i na maka o na kahuna, Aole i aloha i na lunakahiko.
17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán; láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
A hiki mai i keia wa, ua maule ko makou mau maka, no ke kokua makehewa ia mai; I ko makou kakali ana, ua kakali makou i ka lahuikanaka hoola ole mai.
18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri, àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́. Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye nítorí òpin wa ti dé.
Hoohalua lakou i ko makou hele ana, I ole ai makou e hele ma na alanui; Ua kokoke ko makou hope, ua piha ko makou mau la, no ka mea, ua hiki mai ko makou hope.
19 Àwọn tí ń lé wa yára ju idì ojú ọ̀run lọ; wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
Ua oi ka mama o ka poe alualu mai ia makou mamua o ko na aeto o ka lani; Ma na mauna lakou i hahai mai ai ia makou, Hoohalua lakou ia makou ma ka waonahele.
20 Ẹni àmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa, ni wọ́n fi tàkúté wọn mú. Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀ ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
O ka hanu o ko makou mau pukaihu, o ka Iehova mea i poniia, Ua hoopioia oia iloko o ko lakou mau lua, Olelo no makou nona, Ma kona malu makou e ola'i iwaena o ko na aina e.
21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu, ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi. Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú; ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
E olioli, a e hauoli hoi, e ke kaikamahine o Edoma, Ka mea e noho la ma ka aina o Uza; E hiki aku no ke kiaha iou la, E inu ana no hoi oe, a e hemo no kou lole.
22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin; kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.
Ua pau kou hoopaiia, e ke kaikamahine o Ziona; Aole ia e lawe hou aku ia oe iloko o ke pio; E hoopai no oia i kou hewa, e ke kaikamahine o Edoma, E hoike aku no oia i kou mau hewa.

< Lamentations 4 >