< Lamentations 4 >

1 Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù, wúrà dídára di àìdán! Òkúta ibi mímọ́ wá túká sí oríta gbogbo òpópó.
Comme l'or est devenu terne! L'or le plus pur a changé! Les pierres du sanctuaire sont déversées à la tête de chaque rue.
2 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye, tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
Les précieux fils de Sion, comparable à de l'or fin, comment ils sont estimés comme des cruches en terre, l'œuvre des mains du potier!
3 Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn bí ògòǹgò ní aginjù.
Même les chacals offrent leur poitrine. Ils nourrissent leurs petits. Mais la fille de mon peuple est devenue cruelle, comme les autruches dans le désert.
4 Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́ lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn; àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
La langue de l'enfant qui allaite s'accroche à la voûte de sa bouche pour la soif. Les jeunes enfants demandent du pain, et personne ne le casse pour eux.
5 Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára di òtòṣì ní òpópó. Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀ ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
Ceux qui mangeaient des mets délicats sont désolés dans les rues. Ceux qui ont été élevés dans la pourpre embrassent des tas de fumier.
6 Ìjìyà àwọn ènìyàn mi tóbi ju ti Sodomu lọ, tí a sí ní ipò ní òjijì láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
Car l'iniquité de la fille de mon peuple est plus grande que le péché de Sodome, qui a été renversé comme en un instant. Aucune main n'a été posée sur elle.
7 Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì, wọ́n sì funfun ju wàrà lọ wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa, ìrísí wọn dàbí safire.
Ses nobles étaient plus purs que la neige. Ils étaient plus blancs que du lait. Ils avaient un corps plus roux que les rubis. Leur polissage était comme du saphir.
8 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú; wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó. Ara wọn hun mọ́ egungun; ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
Leur apparence est plus noire qu'un charbon. Ils ne sont pas connus dans les rues. Leur peau s'accroche à leurs os. Il est flétri. Il est devenu comme du bois.
9 Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn ju àwọn tí ìyàn pa; tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
Ceux qui sont tués par l'épée sont meilleurs que ceux qui sont tués par la faim; pour ceux qui dépérissent, frappés de plein fouet, par manque de fruits des champs.
10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ tí ó di oúnjẹ fún wọn nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Les mains des femmes pitoyables ont fait bouillir leurs propres enfants. Ils ont servi de nourriture dans la destruction de la fille de mon peuple.
11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀; ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde. Ó da iná ní Sioni tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
Yahvé a accompli sa colère. Il a déversé sa féroce colère. Il a allumé un feu dans Sion, qui a dévoré ses fondations.
12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́, tàbí àwọn ènìyàn ayé, wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ odi ìlú Jerusalẹmu.
Les rois de la terre n'ont pas cru, ni tous les habitants du monde, que l'adversaire et l'ennemi entreraient par les portes de Jérusalem.
13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà, tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
C'est à cause des péchés de ses prophètes. et les iniquités de ses prêtres, qui ont versé le sang des justes au milieu d'elle.
14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó bí ọkùnrin tí ó fọ́jú. Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
Ils errent comme des aveugles dans les rues. Ils sont pollués par le sang, Pour que les hommes ne puissent pas toucher leurs vêtements.
15 “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn. “Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!” Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé, “Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
« Allez-vous-en! » leur crièrent-ils. « Impur! Partez! Partez! Ne pas toucher! Quand ils se sont enfuis et ont erré, les hommes ont dit parmi les nations, « Ils ne peuvent plus vivre ici. »
16 Olúwa ti tú wọn ká fúnra rẹ̀; kò sí bojútó wọn mọ́. Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́, àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
La colère de Yahvé les a dispersés. Il ne leur prêtera plus attention. Ils ne respectaient pas les personnes des prêtres. Ils n'ont pas favorisé les anciens.
17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán; láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
Nos yeux sont toujours défaillants, cherchant en vain notre aide. Dans notre observation, nous avons observé une nation qui ne pouvait pas sauver.
18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri, àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́. Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye nítorí òpin wa ti dé.
Ils chassent nos pas, pour que nous ne puissions pas aller dans nos rues. Notre fin est proche. Nos jours sont accomplis, car notre fin est arrivée.
19 Àwọn tí ń lé wa yára ju idì ojú ọ̀run lọ; wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
Nos poursuivants étaient plus rapides que les aigles du ciel. Ils nous ont poursuivis dans les montagnes. Ils nous ont tendu une embuscade dans le désert.
20 Ẹni àmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa, ni wọ́n fi tàkúté wọn mú. Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀ ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Le souffle de nos narines, l'oint de Yahvé, a été prise dans leurs fosses; dont nous avons dit, sous son ombre, nous vivrons parmi les nations.
21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu, ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi. Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú; ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
Réjouis-toi et sois heureuse, fille d'Édom, qui habite le pays d'Uz. La coupe vous sera également transmise. Tu seras ivre, et tu te mettras à nu.
22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin; kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.
Le châtiment de ton iniquité est accompli, fille de Sion. Il ne vous emmènera plus en captivité. Il visitera ton iniquité, fille d'Édom. Il va découvrir vos péchés.

< Lamentations 4 >