< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Алеф. Аз муж видя нищету (мою) в жезле ярости Его на мя:
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
поят мя и отведе мя во тму, а не во свет.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Обаче на мя обрати руку Свою весь день,
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
беф. Обетши плоть мою и кожу мою, кости моя сокруши:
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
согради на мя и объя главу мою и утруди,
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
в темных посади мя, якоже мертвыя века:
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
гимель. Согради на мя, и не изыду, отяготи оковы моя,
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
и егда воскричу и возопию, загради молитву мою:
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
возгради пути моя, загради стези моя, возмяте.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Далеф. Бысть яко медведь ловяй, (приседяй ми) яко лев в сокровенных,
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
гна отступившаго, и упокои мя, положи мя погибша:
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
напряже лук Свои, и постави мя яко знамение на стреляние,
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
ге. Пусти в лядвия моя стрелы тула Своего.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Бых в смех всем людем моим, песнь их весь день.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Насыти мя горести, напои мя желчи
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
вав. И изя каменем зубы моя, напита мя пепелом
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
и отрину от мира душу мою. Забых благоты
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
и рех: погибе победа моя и надежда моя от Господа.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Заин. Помяни нищету мою и гонение мое.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Горесть и желчь мою помяну, и стужит во мне душа моя.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Сия положу в сердцы моем, сего ради потерплю.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
Иф. Милость Господня, яко не остави мене, не скончашася бо щедроты Его: пребываяй во утриих, помилуй, Господи, яко не погибохом, не скончашася бо щедроты Твоя.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
Новая во утриих, многа есть вера Твоя.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Часть моя Господь, рече душа моя: сего ради пожду Его.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Теф. Благ Господь надеющымся Нань:
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
души ищущей Его благо (есть), и надеющейся с молчанием спасения Божия.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Благо есть мужу, егда возмет ярем в юности своей:
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
иод. Сядет на едине и умолкнет, яко воздвигну на ся:
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
положит во прахе уста своя, негли како будет надежда:
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
подаст ланиту свою биющему, насытится укоризн.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Каф. Яко не во век отринет Господь,
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
яко смиривый помилует по множеству милости Своея,
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
не отрину от сердца Своего и смири сыны мужеския.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Ламед. Еже смирити под нозе его вся узники земныя,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
еже уклонити суд мужа пред лицем Вышняго,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
осудити человека, внегда судитися ему, Господь не рече.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Мем. Кто есть той, иже рече, и быти, Господу не повелевшу?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Из уст Вышняго не изыдет зло и добро.
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Что возропщет человек живущь, муж о гресе своем?
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Нун. Изыскася путь наш и испытася, и обратимся ко Господу.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Воздвигнем сердца наша с руками к Богу высокому на небеси.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
Мы согрешихом и нечествовахом, сего ради не помиловал еси:
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
самех. Покрыл еси яростию и отгнал еси нас, убил и не пощадел еси:
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
покрылся еси облаком, да не дойдет к Тебе молитва,
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
сомжити очи мои и отринути, положил еси нас посреде людий.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Аин. Отверзоша на ны уста своя вси врази наши.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Страх и ужас бысть нам, надмение и сокрушение:
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
исходища водная излиет око мое о сокрушении дщере людий моих.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Фи. Око мое погрязну: и не умолкну, еже не быти ослаблению,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
дондеже приклонится и увидит Господь с небесе.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Око мое закрывается о души моей, паче всех дщерей града.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Цади. Ловяще уловиша мя яко врабия врази мои туне:
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
умориша в рове жизнь мою и возложиша на мя камень.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Возлияся вода выше главы моея: рех: отриновен есмь.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
Коф. Призвах имя Твое, Господи, из рова преисподняго:
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
глас мой услышал еси: не покрый ушес Твоих на мольбу мою:
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
на помощь мою приближился еси, в день, в оньже призвах Тя, рекл ми еси: не бойся.
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Реш. Судил еси, Господи, прю души моея, избавил еси жизнь мою:
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
видел еси, Господи, смятения моя, разсудил еси суд мой:
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
веси все отмщение их и вся помышления их на мя.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Шин. Слышал еси укоризны их, вся советы их на мя,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
устне востающих на мя и поучение их на мя весь день,
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
седение их и востание их: призри на очи их.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Фав. Воздаси им, Господи, воздаяние по делом руку их:
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
воздаси им заступление, сердца моего труд.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Ты их проженеши во гневе и потребиши их под небесем, Господи.

< Lamentations 3 >