< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Я человек, испытавший горе от жезла гнева Его.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Он повел меня и ввел во тьму, а не во свет.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Так, Он обратился на меня и весь день обращает руку Свою;
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
измождил плоть мою и кожу мою, сокрушил кости мои;
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
огородил меня и обложил горечью и тяготою;
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
посадил меня в темное место, как давно умерших;
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
окружил меня стеною, чтобы я не вышел, отяготил оковы мои,
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
и когда я взывал и вопиял, задерживал молитву мою;
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
каменьями преградил дороги мои, извратил стези мои.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Он стал для меня как бы медведь в засаде, как бы лев в скрытном месте;
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
извратил пути мои и растерзал меня, привел меня в ничто;
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
натянул лук Свой и поставил меня как бы целью для стрел;
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
послал в почки мои стрелы из колчана Своего.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Я стал посмешищем для всего народа моего, вседневною песнью их.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Он пресытил меня горечью, напоил меня полынью.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Сокрушил камнями зубы мои, покрыл меня пеплом.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
И удалился мир от души моей; я забыл о благоденствии,
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
и сказал я: погибла сила моя и надежда моя на Господа.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Помысли о моем страдании и бедствии моем, о полыни и желчи.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Твердо помнит это душа моя и падает во мне.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Вот что я отвечаю сердцу моему и потому уповаю:
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
по милости Господа мы не исчезли, ибо милосердие Его не истощилось.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
Оно обновляется каждое утро; велика верность Твоя!
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Господь часть моя, говорит душа моя, итак буду надеяться на Него.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Благ Господь к надеющимся на Него, к душе, ищущей Его.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Благо тому, кто терпеливо ожидает спасения от Господа.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Благо человеку, когда он несет иго в юности своей;
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
сидит уединенно и молчит, ибо Он наложил его на него;
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
полагает уста свои в прах, помышляя: “может быть, еще есть надежда”;
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
подставляет ланиту свою биющему его, пресыщается поношением,
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
ибо не навек оставляет Господь.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
Но послал горе, и помилует по великой благости Своей.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
Ибо Он не по изволению сердца Своего наказывает и огорчает сынов человеческих.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Но, когда попирают ногами своими всех узников земли,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
когда неправедно судят человека пред лицoм Всевышнего,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
когда притесняют человека в деле его: разве не видит Господь?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Кто это говорит: “и то бывает, чему Господь не повелел быть”?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Не от уст ли Всевышнего происходит бедствие и благополучие?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Зачем сетует человек живущий? всякий сетуй на грехи свои.
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Испытаем и исследуем пути свои, и обратимся к Господу.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Вознесем сердце наше и руки к Богу, сущему на небесах:
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
мы отпали и упорствовали; Ты не пощадил.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Ты покрыл Себя гневом и преследовал нас, умерщвлял, не щадил;
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Ты закрыл Себя облаком, чтобы не доходила молитва наша;
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
сором и мерзостью Ты сделал нас среди народов.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Разинули на нас пасть свою все враги наши.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Ужас и яма, опустошение и разорение - доля наша.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Потоки вод изливает око мое о гибели дщери народа моего.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Око мое изливается и не перестает, ибо нет облегчения,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
доколе не призрит и не увидит Господь с небес.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Око мое опечаливает душу мою ради всех дщерей моего города.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Всячески усиливались уловить меня, как птичку, враги мои, без всякой причины;
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
повергли жизнь мою в яму и закидали меня камнями.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Воды поднялись до головы моей; я сказал: “погиб я”.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
Я призывал имя Твое, Господи, из ямы глубокой.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Ты слышал голос мой; не закрой уха Твоего от воздыхания моего, от вопля моего.
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Ты приближался, когда я взывал к Тебе, и говорил: “не бойся”.
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Ты защищал, Господи, дело души моей; искуплял жизнь мою.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Ты видишь, Господи, обиду мою; рассуди дело мое.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Ты видишь всю мстительность их, все замыслы их против меня.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Ты слышишь, Господи, ругательство их, все замыслы их против меня,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
речи восстающих на меня и их ухищрения против меня всякий день.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Воззри, сидят ли они, встают ли, я для них - песнь.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Воздай им, Господи, по делам рук их;
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
пошли им помрачение сердца и проклятие Твое на них;
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
преследуй их, Господи, гневом, и истреби их из поднебесной.

< Lamentations 3 >