< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Jam jest ten mąż, którym widział utrapienie od rózgi rozgniewania Bożego.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Zaprowadził mię, i zawiódł do ciemności, a nie do światłości;
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Tylko się na mię obórzył, a obrócił rękę swoję przez cały dzień.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Do starości przywiódł ciało moje i skórę moję, a połamał kości moje.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Obudował mię a ogarnął żółcią i pracą;
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
W ciemnych miejscach posadził mię, jako tych, którzy dawno pomarli.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Ogrodził mię, abym nie wyszedł, obciążył okowy moje;
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
A choć wołam i krzyczę, zatula uszy na modlitwę moję.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
Ogrodził drogę moję ciosanym kamieniem, ścieszki moje wywrócił.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Jest jako niedźwiedziem czyhającym na mię, jako lwem w skrytościach.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
Drogi moje odwrócił, owszem, rozszarpał mię, i uczynił mię spustoszoną.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
Naciągnął łuk swój, a postawił mię jako cel strzałom swym.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
Przestrzelił nerki moje strzałami z sajdaka swego.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Jestem pośmiewiskiem ze wszystkim ludem moim, pieśnią ich przez cały dzień.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Nasyca mię gorzkościami; upija mię piołunem.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Nadto pokruszył o kamyczki zęby moje, i pogrążył mię w popiele.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Takeś oddalił, o Boże! od pokoju duszę moję, aż na wczasy zapominam.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
I mówię: Zginęła siła moja, i nadzieja moja, którąm miał w Panu.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Wszakże wspominając na utrapienie moje, i na płacz mój, na piołun, i na żółć.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Wspominając ustawicznie, uniża się we mnie dusza moja.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Przywodząc to sobie do serca swego, mam nadzieję.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
Wielkie jest miłosierdzie Pańskie, żeśmy do szczętu nie zginęli; nie ustawają zaiste litości jego.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
Ale się na każdy poranek odnawiają; wielka jest prawda twoja.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Pan jest działem moim, mówi dusza moja, dlatego mam w nim nadzieję.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Dobry jest Pan tym, którzy nań oczekują, duszy takowej, która go szuka.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Dobrze jest, cierpliwie oczekiwać na zbawienie Pańskie.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Dobrze jest mężowi nosić jarzmo od dzieciństwa swego;
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
Który będąc opuszczony, cierpliwym jest w tem, co nań włożono;
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
Kładzie w prochu usta swe, ażby się okazała nadzieja;
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Nadstawia bijącemu policzka, a nasycony bywa obelżeniem.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Bo Pan na wieki nie odrzuca;
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
Owszem, jeźli zasmuca, zasię się zmiłuje według mnóstwa miłosierdzia swego.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
Zaiste nie z serca trapi i zasmuca synów ludzkich.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Aby kto starł nogami swemi wszystkich więźniów w ziemi;
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
Aby kto niesprawiedliwie sądził męża przed obliczem Najwyższego;
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
Aby kto wywrócił człowieka w sprawie jego, Pan się w tem nie kocha.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Któż jest, coby rzekł: Stało się, a Pan nie przykazał?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Izali z ust Najwyższego nie pochodzi złe i dobre?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Przeczżeby tedy sobie utyskiwać miał człowiek żyjący, a mąż nad kaźnią za grzechy swoje.
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Dowiadujmy się raczej, a badajmy się dróg naszych, nawróćmy się do Pana;
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Podnieśmy serca i ręce nasze w niebo do Boga.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
Myśmy wstąpili i staliśmy się odpornymi; przetoż ty nie odpuszczasz.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Okryłeś się zapalczywością, i gonisz nas, mordujesz, a nie szanujesz.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Okryłeś się obłokiem, aby cię nie dochodziła modlitwa.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Za śmieci i za pomiotło położyłeś nas w pośrodku tych narodów.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Otworzyli na nas usta swoje wszyscy nieprzyjaciele nasi.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Strach i dół przyszedł na nas, spustoszenie i skruszenie.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Strumienie wód płyną z oczów moich, dla skruszenia córki ludu mojego.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Oczy moje płyną bez przestanku, przeto, że niemasz żadnej ulgi,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Ażby wejrzał i obaczył Pan z nieba.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Oczy moje trapią duszę moję dla wszystkich córek miasta mojego.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Łowili mię ustawicznie jako ptaka nieprzyjaciele moi bez przyczyny.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
Wrzucili do dołu żywot mój, a przywalili mię kamieniem.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Wezbrały wody nad głową moją, i rzekłem: Jużci po mnie!
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
Wzywam imienia twego, o Panie! z dołu bardzo głębokiego.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Głos mój wysłuchiwałeś; nie zatulajże ucha twego przed wzdychaniem mojem, i przed wołaniem mojem.
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Przybliżając się do mnie w dzień, któregom cię wzywał, mawiałeś: Nie bój się.
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Zastawiałeś się, Panie! o sprawę duszy mojej, a wybawiałeś żywot mój.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Widzisz, o Panie! bezprawie, które mi się dzieje, osądźże sprawę moję.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Widzisz wszystkę pomstę ich, i wszystkie zamysły ich przeciwko mnie.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Słyszysz urąganie ich, o Panie! i wszystkie zamysły ich przeciwko mnie.
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
Słyszysz wargi powstawających przeciwko mnie, i przemyśliwanie ich przeciwko mnie przez cały dzień.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Obacz siadanie ich, i wstawanie ich; jam zawżdy jest pieśnią ich.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Oddajże im nagrodę, Panie! według sprawy rąk ich;
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Dajże im zatwardziałe serce, i przeklęstwo swe na nich;
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Goń ich w zapalczywości, a zgładź ich, aby nie byli pod niebem twojem, o Panie!

< Lamentations 3 >