< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Jeg er den mann som har sett elendighet under hans vredes ris.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Mig har han ledet og ført i mørke og ikke i lys.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Bare mot mig vender han atter og atter sin hånd den hele dag.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Han lot mitt kjøtt og min hud fortæres; han knuste mine ben.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Han bygget en mur mot mig og omringet mig med bitterhet og møie.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
På mørke steder lot han mig bo som de for lenge siden døde.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Han murte igjen for mig, så jeg ikke kan komme ut; han gjorde mine lenker tunge.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Om jeg enn ropte og skrek, lukket han sitt øre for min bønn.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
Han tilmurte mine veier med hugne stener, mine stier gjorde han krokete.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
En lurende bjørn var han mot mig, en løve i skjul.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
Mine veier gjorde han til avveier, han sønderrev mig og ødela mig.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
Han spente sin bue og stilte mig op til mål for sin pil.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
Han lot sitt koggers sønner fare inn i mine nyrer.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Jeg er blitt til latter for alt mitt folk, til en spottesang for dem hele dagen.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Han mettet mig med bitre urter, han gav mig rikelig malurt å drikke.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Han knuste mine tenner, han gav mig småsten å ete, han trykte mig ned i asken.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Du forkastet mig og tok bort min fred; jeg glemte det som godt er,
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
og jeg sa: Det er forbi med min kraft og mitt håp til Herren.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Kom i hu min elendighet og min landflyktighet - malurt og galle!
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Min sjel kommer det i hu og er nedbøiet i mig.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Dette vil jeg ta mig til hjerte, derfor vil jeg håpe:
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
Herrens miskunnhet er det at det ikke er forbi med oss; for hans barmhjertighet har ennu ikke ende.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
Den er ny hver morgen, din trofasthet er stor.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Herren er min del, sier min sjel; derfor håper jeg på ham.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Herren er god mot dem som bier efter ham, mot den sjel som søker ham.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Det er godt at en bier i stillhet efter Herrens frelse.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Det er godt for en mann at han bærer åk i sin ungdom,
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
at han sitter ene og tier, når han legger byrder på ham,
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
at han trykker sin munn i støvet og sier: Kanskje det ennu er håp -
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
at han vender sitt kinn til den som slår ham, lar sig mette med hån.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
For Herren forkaster ikke til evig tid,
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
men om han bedrøver, så forbarmer han sig igjen efter sin rike miskunnhet;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
for det er ikke av hjertet han plager eller bedrøver menneskenes barn.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Når nogen knuser alle jordens fanger under sine føtter,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
bøier mannens rett for den Høiestes åsyn
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
eller gjør en mann urett i hans sak - mon Herren ikke ser det?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Hvem talte så det skjedde, uten at Herren bød det?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Er det ikke fra den Høiestes munn både de onde og de gode ting utgår?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Hvorfor klager et menneske som lever? Enhver klage over sin egen synd!
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
La oss ransake våre veier og granske dem, og la oss vende om til Herren!
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
La oss løfte vårt hjerte og våre hender til Gud i himmelen!
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
Vi har syndet og vært gjenstridige; du har ikke tilgitt.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Du innhyllet dig i vrede og forfulgte oss; du slo ihjel, du sparte ikke.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Du innhyllet dig i skyer, så ingen bønn trengte igjennem.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Til skarn og utskudd gjorde du oss midt iblandt folkene.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
De spilte op sin munn mot oss alle våre fiender.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Gru og grav er blitt oss til del, ødeleggelse og undergang.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Bekker av tårer rinner fra mitt øie fordi mitt folks datter er gått under.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mitt øie rinner og har ikke ro, det får ingen hvile,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
før Herrens øie ser ned fra himmelen.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Mitt øie volder min sjel smerte for alle min stads døtres skyld.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Hårdt jaget de mig som en fugl de som var mine fiender uten årsak.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
De vilde gjøre ende på mitt liv, de vilde kaste mig i brønnen, og de kastet sten på mig.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Vannene strømmet over mitt hode; jeg sa: Jeg er fortapt.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
Jeg påkalte ditt navn, Herre, fra den dypeste brønn.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Du hørte min røst; lukk ikke ditt øre for mitt rop, men la mig få lindring!
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Du var nær den dag jeg kalte på dig; du sa: Frykt ikke!
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Herre, du har ført min sjels sak, du har frelst mitt liv.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Herre, du har sett den urett jeg har lidt; døm i min sak!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Du har sett all deres hevn, alle deres onde råd mot mig.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Du har hørt deres hån, Herre, alle deres onde råd mot mig,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
mine motstanderes tale og deres tanker mot mig den hele dag.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Akt på dem når de sitter, og når de står op! De synger spottesanger om mig.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Du vil gjøre gjengjeld mot dem, Herre, efter deres henders gjerning.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Du vil legge et dekke over deres hjerte, din forbannelse vil bli dem til del.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Du vil forfølge dem i vrede og ødelegge dem, så de ikke mere finnes under Herrens himmel.

< Lamentations 3 >