< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Ich bin ein elender Mann, der die Rute seines Grimmes sehen muß.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Er hat mich geführet und lassen gehen in die Finsternis und nicht ins Licht.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Er hat seine Hand gewendet wider mich und handelt gar anders mit mir für und für.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Er hat mein Fleisch und Haut alt gemacht und mein Gebein zerschlagen.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Er hat mich verbauet und mich mit Galle und Mühe umgeben.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
Er hat mich in Finsternis gelegt, wie die Toten in der Welt.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Er hat mich vermauert, daß ich nicht heraus kann, und mich in harte Fesseln gelegt.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Und wenn ich gleich schreie und rufe, so stopft er die Ohren zu vor meinem Gebet.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
Er hat meinen Weg vermauert mit Werkstücken und meinen Steig umgekehret.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Er hat auf mich gelauert wie ein Bär, wie ein Löwe im Verborgenen.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
Er läßt mich des Weges fehlen. Er hat mich zerstücket und zunichte gemacht.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
Er hat seinen Bogen gespannet und mich dem Pfeil zum Ziel gesteckt.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
Er hat aus dem Köcher in meine Nieren schießen lassen.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Ich bin ein Spott allem meinem Volk und täglich ihr Liedlein.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Er hat mich mit Bitterkeit gesättiget und mit Wermut getränket.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Er hat meine Zähne zu kleinen Stücken zerschlagen. Er wälzet mich in der Asche.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Meine Seele ist aus dem Frieden vertrieben; ich muß des Guten vergessen.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
Ich sprach: Mein Vermögen ist dahin und meine Hoffnung am HERRN.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Gedenke doch, wie ich so elend und verlassen, mit Wermut und Galle getränket bin.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Du wirst ja daran gedenken, denn meine Seele sagt mir's.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Das nehme ich zu Herzen, darum hoffe ich noch.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
Die Gute des HERRN ist, daß wir nicht gar aus sind; seine Barmherzigkeit hat noch kein Ende,
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
sondern sie ist alle Morgen neu, und deine Treue ist groß.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Der HERR ist mein Teil, spricht meine Seele, darum will ich auf ihn hoffen.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Denn der HERR ist freundlich dem, der auf ihn harret, und der Seele, die nach ihm fraget.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Es ist ein köstlich Ding, geduldig sein und auf die Hilfe des HERRN hoffen.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Es ist ein köstlich Ding einem Manne, daß er das Joch in seiner Jugend trage,
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
daß ein Verlassener geduldig sei, wenn ihn etwas überfällt,
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
und seinen Mund in den Staub stecke und der Hoffnung erwarte
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
und lasse sich auf die Backen schlagen und ihm viel Schmach anlegen.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Denn der HERR verstößt nicht ewiglich,
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
sondern er betrübet wohl und erbarmet sich wieder nach seiner großen Güte;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
denn er nicht von Herzen die Menschen plaget und betrübet,
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
als wollte er alle die Gefangenen auf Erden gar unter seine Füße zertreten
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
und eines Mannes Recht vor dem Allerhöchsten beugen lassen
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
und eines Menschen Sache verkehren lassen, gleich als sähe es der HERR nicht.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Wer darf denn sagen, daß solches geschehe ohne des HERRN Befehl,
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
und daß weder Böses noch Gutes komme aus dem Munde des Allerhöchsten?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Wie murren denn die Leute im Leben also? Ein jeglicher murre wider seine Sünde!
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Und laßt uns forschen und suchen unser Wesen und uns zum HERRN bekehren.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Laßt uns unser Herz samt den Händen aufheben zu Gott im Himmel.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
Wir, wir haben gesündiget und sind ungehorsam gewesen. Darum hast du billig nicht verschonet,
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
sondern du hast uns mit Zorn überschüttet und verfolget und ohne Barmherzigkeit erwürget.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Du hast dich mit einer Wolke verdeckt, daß kein Gebet hindurch konnte.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Du hast uns zu Kot und Unflat gemacht unter den Völkern.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Alle unsere Feinde sperren ihr Maul auf wider uns.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Wir werden gedrückt und geplagt mit Schrecken und Angst.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Meine Augen rinnen mit Wasserbächen über dem Jammer der Tochter meines Volks.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Meine Augen fließen und können nicht ablassen; denn es ist kein Aufhören da,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
bis der HERR vom Himmel herabschaue und sehe darein.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Mein Auge frißt mir das Leben weg um die Tochter meiner Stadt.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Meine Feinde haben mich gehetzet, wie einen Vogel, ohne Ursache.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
Sie haben mein Leben in einer Grube umgebracht und Steine auf mich geworfen.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Sie haben auch mein Haupt mit Wasser überschüttet. Da sprach ich: Nun bin ich gar dahin.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
Ich rief aber deinen Namen an, HERR, unten aus der Grube;
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
und du erhöretest meine Stimme. Verbirg deine Ohren nicht vor meinem Seufzen und Schreien!
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Nahe dich zu mir, wenn ich dich anrufe, und sprich: Fürchte dich nicht!
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Führe du, HERR, die Sache meiner Seele und erlöse mein Leben!
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
HERR, schaue, wie mir so unrecht geschieht, und hilf mir zu meinem Recht!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Du siehest alle ihre Rache und alle ihre Gedanken wider mich.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
HERR, du hörest ihre Schmach und alle ihre Gedanken über mich,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
die Lippen meiner Widerwärtigen und ihr Dichten wider mich täglich.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Schaue doch; sie gehen nieder oder stehen auf, so singen sie von mir Liedlein.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Vergilt ihnen, HERR, wie sie verdienet haben!
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Laß ihnen das Herz erschrecken und deinen Fluch fühlen!
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Verfolge sie mit Grimm und vertilge sie unter dem Himmel des HERRN!

< Lamentations 3 >