< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Je suis l'homme qui a senti le malheur sous la verge de sa colère.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Il m'a poussé, engagé dans les ténèbres, et non dans la lumière.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Oui, tous les jours Il revient à la charge, et tourne sa a main contre moi.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Il a usé ma chair et ma peau, Il a brisé mes os.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Il m'a cerné, et m'a enveloppé d'amertume et de malaise.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
Il m'a fait entrer dans les lieux sombres, comme ceux qui dès longtemps sont morts.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Il m'a parqué, pour que je n'aie point d'issue, Il a fait peser sur moi les fers.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Que je crie, que j'appelle du secours, Il ne donne pas accès à ma prière.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
Il a muré mes voies de pierres massives, et ruiné mes sentiers.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Il est pour moi l'ourse qui se tient aux aguets, le lion posté en embuscade.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
Il a fait dévier mes voies, et Il m'a déchiré, Il m'a ravagé.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
Il a bandé son arc, et m'a placé comme un but à ses traits.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
Il a percé mes reins des flèches de son carquois.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Je suis la risée de tout mon peuple, et leur chanson tout le long du jour.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Il m'a rassasié d'amertume, Il m'a abreuvé d'absinthe.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Il a broyé mes dents avec le caillou, Il m'a plongé dans la cendre.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Tu as fait déchoir mon âme du salut, j'ai oublié le bonheur,
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
et je dis: C'en est fait de la confiance et de l'espérance que j'avais dans l'Éternel.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Souviens-toi de ma misère et de mon tourment, des herbes amères et vénéneuses!
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
A ces souvenirs, mon âme s'abat au dedans de moi.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Voici ce dont je pénètre mon cœur, et par là je garderai l'espérance:
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
« C'est à la grâce de l'Éternel que [nous devons] de n'être pas anéantis; car ses miséricordes ne s'épuisent pas;
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
elles sont tous les jours nouvelles, ta fidélité est immense. »
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
L'Éternel est mon lot, ainsi parle mon âme; aussi j'espère en Lui.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
L'Éternel est plein de bonté pour ceux qui l'attendent, pour l'âme qui le cherche.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Il est bon d'attendre avec calme le secours de l'Éternel.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Il est bon à l'homme de porter le joug dès sa jeunesse;
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
de s'asseoir solitaire et silencieux, quand Il lui impose un fardeau,
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
de baiser de sa bouche la poussière [en disant: ] Peut-être y a-t-il de l'espoir!
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
de présenter la joue à qui veut le frapper, de se laisser abreuver d'outrages.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Car le Seigneur ne rejette pas pour jamais;
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
car s'il afflige, Il prend pitié dans sa grande miséricorde;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
car ce n'est pas volontiers qu'il humilie et afflige les enfants des hommes.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Quand on foule aux pieds tous les captifs de la terre,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
quand on prévarique dans le jugement d'un homme la face du Très-Haut;
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
quand on fait tort à un humain dans sa cause, le Seigneur ne le voit-Il pas?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
A la parole de qui une chose paraît-elle, sans l'ordre du Seigneur?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Le malheur et le bonheur ne viennent-ils pas de la bouche du Très-Haut?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Pourquoi l'homme accuse-t-il la vie? que chacun s'en prenne à ses propres péchés!
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Examinons nos voies et les sondons, et retournons à l'Éternel!
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Élevons nos cœurs en même temps que nos mains vers Dieu qui est dans le ciel.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
Nous avons péché, et nous fûmes rebelles; tu ne pardonnas pas.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Irrité, tu te cachas, et tu nous poursuivis, tu massacras, et tu fus impitoyable.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Tu t'enveloppas dans la nue pour être inaccessible à notre prière.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Tu nous as mis comme des balayures et un opprobre au milieu des nations.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Tous nos ennemis ouvrent contre nous une large bouche.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Nous avons eu pour nous la terreur et la fosse, le ravage et la ruine.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Des torrents d'eau tombent de mes yeux à cause de la ruine de la fille de mon peuple.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mes yeux ruissellent sans trêve ni relâche,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
jusqu'à ce que des Cieux l'Éternel regarde et voie;
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
mes yeux me font souffrir à cause de toutes les filles de ma cité.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Ceux qui me sont gratuitement hostiles, m'ont donné la chasse comme à l'oiseau;
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
ils ont voulu m'arracher la vie dans la fosse, et ils m'ont lapidé;
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
les eaux m'ont submergé jusqu'au-dessus de la tête; je disais: C'en est fait de moi!
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
J'invoquai ton nom, Éternel, du fond de la fosse;
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
tu entendis ma voix: ne dérobe pas ton oreille à mes cris, afin de me délivrer!
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Tu t'approches, quand je t'implore, tu m'as dit: Sois sans peur!
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Seigneur, tu soutiens ma querelle, tu rachètes ma vie.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Tu vois, Éternel, le tort qu'on me fait: sois juge de ma cause!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Tu vois toutes leurs vengeances, tous les plans qu'ils forment contre moi.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Tu entends leurs outrages, Éternel, et les plans qu'ils forment contre moi,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
les propos de mes adversaires, et les pensées qu'ils nourrissent contre moi tout le jour.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Suis-les, quand ils sont assis, et quand ils se lèvent! je suis leur chanson.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Paie-leur, Éternel, un salaire conforme aux actes de leurs mains.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Donne-leur l'endurcissement du cœur: que ta malédiction soit pour eux!
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Poursuis-les dans la colère, et fais-les disparaître de dessous les Cieux de l'Éternel!

< Lamentations 3 >