< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Je suis l’homme qui a vu la misère Sous la verge de sa fureur.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Il m’a conduit, mené dans les ténèbres, Et non dans la lumière.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Contre moi il tourne et retourne sa main Tout le jour.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Il a fait dépérir ma chair et ma peau, Il a brisé mes os.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Il a bâti autour de moi, Il m’a environné de poison et de douleur.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
Il me fait habiter dans les ténèbres, Comme ceux qui sont morts dès longtemps.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Il m’a entouré d’un mur, pour que je ne sorte pas; Il m’a donné de pesantes chaînes.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
J’ai beau crier et implorer du secours, Il ne laisse pas accès à ma prière.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
Il a fermé mon chemin avec des pierres de taille, Il a détruit mes sentiers.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Il a été pour moi un ours en embuscade, Un lion dans un lieu caché.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
Il a détourné mes voies, il m’a déchiré, Il m’a jeté dans la désolation.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
Il a tendu son arc, et il m’a placé Comme un but pour sa flèche.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
Il a fait entrer dans mes reins Les traits de son carquois.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Je suis pour tout mon peuple un objet de raillerie, Chaque jour l’objet de leurs chansons.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Il m’a rassasié d’amertume, Il m’a enivré d’absinthe.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Il a brisé mes dents avec des cailloux, Il m’a couvert de cendre.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Tu m’as enlevé la paix; Je ne connais plus le bonheur.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
Et j’ai dit: Ma force est perdue, Je n’ai plus d’espérance en l’Éternel!
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Quand je pense à ma détresse et à ma misère, A l’absinthe et au poison;
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Quand mon âme s’en souvient, Elle est abattue au-dedans de moi.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Voici ce que je veux repasser en mon cœur, Ce qui me donnera de l’espérance.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
Les bontés de l’Éternel ne sont pas épuisées, Ses compassions ne sont pas à leur terme;
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
Elles se renouvellent chaque matin. Oh! Que ta fidélité est grande!
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
L’Éternel est mon partage, dit mon âme; C’est pourquoi je veux espérer en lui.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
L’Éternel a de la bonté pour qui espère en lui, Pour l’âme qui le cherche.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Il est bon d’attendre en silence Le secours de l’Éternel.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Il est bon pour l’homme De porter le joug dans sa jeunesse.
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
Il se tiendra solitaire et silencieux, Parce que l’Éternel le lui impose;
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
Il mettra sa bouche dans la poussière, Sans perdre toute espérance;
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Il présentera la joue à celui qui le frappe, Il se rassasiera d’opprobres.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Car le Seigneur Ne rejette pas à toujours.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
Mais, lorsqu’il afflige, Il a compassion selon sa grande miséricorde;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
Car ce n’est pas volontiers qu’il humilie Et qu’il afflige les enfants des hommes.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Quand on foule aux pieds Tous les captifs du pays,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
Quand on viole la justice humaine A la face du Très-Haut,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
Quand on fait tort à autrui dans sa cause, Le Seigneur ne le voit-il pas?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Qui dira qu’une chose arrive, Sans que le Seigneur l’ait ordonnée?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
N’est-ce pas de la volonté du Très-Haut que viennent Les maux et les biens?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Pourquoi l’homme vivant se plaindrait-il? Que chacun se plaigne de ses propres péchés.
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Recherchons nos voies et sondons, Et retournons à l’Éternel;
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Élevons nos cœurs et nos mains Vers Dieu qui est au ciel:
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
Nous avons péché, nous avons été rebelles! Tu n’as point pardonné!
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Tu t’es caché dans ta colère, et tu nous as poursuivis; Tu as tué sans miséricorde;
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Tu t’es enveloppé d’un nuage, Pour fermer accès à la prière.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Tu nous as rendus un objet de mépris et de dédain Au milieu des peuples.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Ils ouvrent la bouche contre nous, Tous ceux qui sont nos ennemis.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Notre partage a été la terreur et la fosse, Le ravage et la ruine.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Des torrents d’eau coulent de mes yeux, A cause de la ruine de la fille de mon peuple.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mon œil fond en larmes, sans repos, Sans relâche,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Jusqu’à ce que l’Éternel regarde et voie Du haut des cieux;
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Mon œil me fait souffrir, A cause de toutes les filles de ma ville.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Ils m’ont donné la chasse comme à un oiseau, Ceux qui sont à tort mes ennemis.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
Ils ont voulu anéantir ma vie dans une fosse, Et ils ont jeté des pierres sur moi.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Les eaux ont inondé ma tête; Je disais: Je suis perdu!
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
J’ai invoqué ton nom, ô Éternel, Du fond de la fosse.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Tu as entendu ma voix: Ne ferme pas l’oreille à mes soupirs, à mes cris!
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Au jour où je t’ai invoqué, tu t’es approché, Tu as dit: Ne crains pas!
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Seigneur, tu as défendu la cause de mon âme, Tu as racheté ma vie.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Éternel, tu as vu ce qu’on m’a fait souffrir: Rends-moi justice!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Tu as vu toutes leurs vengeances, Tous leurs complots contre moi.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Éternel, tu as entendu leurs outrages, Tous leurs complots contre moi,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
Les discours de mes adversaires, et les projets Qu’ils formaient chaque jour contre moi.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Regarde quand ils sont assis et quand ils se lèvent: Je suis l’objet de leurs chansons.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Tu leur donneras un salaire, ô Éternel, Selon l’œuvre de leurs mains;
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Tu les livreras à l’endurcissement de leur cœur, A ta malédiction contre eux;
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Tu les poursuivras dans ta colère, et tu les extermineras De dessous les cieux, ô Éternel!

< Lamentations 3 >