< Lamentations 3 >
1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Mi estas la viro, kiu spertis suferon sub la vergo de Lia kolero.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Min Li kondukis kaj irigis en mallumon, ne en lumon.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Nur sur min Li turnas Sian manon ĉiutage denove.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Li maljunigis mian karnon kaj haŭton, rompis miajn ostojn.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Li konstruis ĉirkaŭ mi, ĉirkaŭis min per maldolĉaĵoj kaj malfacilaĵoj.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
En mallumon Li lokis min, kiel porĉiamajn mortintojn.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Li ĉirkaŭbaris min, ke mi ne povu eliri; Li ligis min per pezaj ĉenoj.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Kvankam mi krias kaj vokas, Li kovras Siajn orelojn antaŭ mia preĝo.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
Li baris miajn vojojn per hakitaj ŝtonoj; Li kurbigis miajn vojetojn.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Li estas por mi kiel urso en embusko, kiel leono en kaŝita loko.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
Li depuŝis min de miaj vojoj, kaj disŝiris min; Li faris min objekto de teruro.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
Li streĉis Sian pafarkon, kaj starigis min kiel celon por Siaj sagoj.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
En miajn renojn Li pafis la filojn de Sia sagujo.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
Mi fariĝis mokataĵo por mia tuta popolo, ilia ĉiutaga rekantaĵo.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
Li satigis min per maldolĉaĵo, trinkoplenigis min per vermuto.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Li disrompis miajn dentojn en malgrandajn pecojn, Li enpuŝis min en cindron.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Mia animo estas forpuŝita for de paco; bonstaton mi forgesis.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
Kaj mi diris: Pereis mia forto kaj mia espero al la Eternulo.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
La memoro pri mia mizero kaj miaj suferoj estas vermuto kaj galo.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Konstante rememorante tion, senfortiĝas en mi mia animo.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Sed tion mi respondas al mia koro, kaj tial mi esperas:
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
Ĝi estas favorkoreco de la Eternulo, ke ni ne tute pereis; ĉar Lia kompatemeco ne finiĝis,
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
Sed ĉiumatene ĝi renoviĝas; granda estas Via fideleco.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Mia parto estas la Eternulo, diras mia animo; tial mi esperas al Li.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
La Eternulo estas bona por tiuj, kiuj esperas al Li, por la animo, kiu serĉas Lin.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Bone estas esperi pacience helpon de la Eternulo.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Bone estas al la homo, kiu portas jugon en sia juneco;
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
Li sidas solece kaj silentas, kiam li estas ŝarĝita;
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
Li metas sian buŝon en polvon, kredante, ke ekzistas espero;
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Li donas sian vangon al tiu, kiu lin batas; li satigas sin per malhonoro.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Ĉar ne por eterne forlasas la Sinjoro;
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
Se Li iun suferigas, Li ankaŭ kompatas pro Sia granda favorkoreco;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
Ĉar ne el Sia koro Li sendas mizeron kaj suferon al la homoj.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Kiam oni premas sub siaj piedoj ĉiujn malliberulojn de la tero,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
Kiam oni forklinas la rajton de homo antaŭ la vizaĝo de la Plejaltulo,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
Kiam oni estas maljusta kontraŭ homo en lia juĝa afero — Ĉu la Sinjoro tion ne vidas?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Kiu povas per sia diro atingi, ke io fariĝu, se la Sinjoro tion ne ordonis?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Ĉu ne el la buŝo de la Plejaltulo eliras la decidoj pri malbono kaj pri bono?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Kial murmuras homo vivanta? Ĉiu murmuru kontraŭ siaj pekoj.
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Ni trarigardu kaj esploru nian konduton, kaj ni revenu al la Eternulo;
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Ni levu nian koron kaj niajn manojn al Dio en la ĉielo.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
Ni pekis kaj malobeis, kaj Vi ne pardonis.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Vi kovris Vin per kolero kaj persekutis nin; Vi mortigis, Vi ne kompatis.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Vi kovris Vin per nubo, por ke ne atingu Vin la preĝo.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Vi faris nin balaindaĵo kaj abomenindaĵo inter la popoloj.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Malfermegis kontraŭ ni sian buŝon ĉiuj niaj malamikoj.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Teruro kaj pereo trafis nin, ruinigo kaj malfeliĉo.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Torentojn da akvo verŝas mia okulo pri la malfeliĉo de la filino de mia popolo.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mia okulo fluigas kaj ne ĉesas, ne ekzistas por ĝi halto,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Ĝis la Eternulo ekrigardos kaj ekvidos de la ĉielo.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Mia okulo suferigas mian animon pri ĉiuj filinoj de mia urbo.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Senkaŭze ĉasas min kiel birdon miaj malamikoj;
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
Ili pereigas mian vivon en kavo, ili ĵetas sur min ŝtonojn.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Akvo leviĝis kontraŭ mian kapon, kaj mi diris: Mi tute pereis.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
Mi vokis Vian nomon, ho Eternulo, el la profunda kavo;
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Vi aŭdis mian voĉon; ne kovru Vian orelon antaŭ mia vokado pri liberigo.
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Vi alproksimiĝis, kiam mi vokis al Vi; Vi diris: Ne timu.
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Vi, ho Sinjoro, defendis mian juĝaferon; Vi liberigis mian vivon.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Vi vidis, ho Eternulo, la maljustaĵon, kiun mi suferas; juĝu mian aferon.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Vi vidis ilian tutan venĝon, ĉiujn iliajn intencojn kontraŭ mi.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Vi aŭdis ilian insultadon, ho Eternulo, ĉiujn iliajn intencojn kontraŭ mi,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
La parolojn de tiuj, kiuj leviĝis kontraŭ min, kaj iliajn pensojn kontraŭ mi dum la tuta tago.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Rigardu, kiam ili sidas kaj kiam ili leviĝas; mi ĉiam estas ilia rekantaĵo.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Redonu al ili repagon, ho Eternulo, laŭ la faroj de iliaj manoj.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Donu al ili doloron en la koro, sentigu al ili Vian malbenon.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Persekutu ilin en kolero, kaj ekstermu ilin el sub la ĉielo de la Eternulo.