< Lamentations 3 >
1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
I [am] the man [who] hath seen affliction By the rod of His wrath.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Me He hath led, and causeth to go [in] darkness, and without light.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Surely against me He turneth back, He turneth His hand all the day.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
He hath worn out my flesh and my skin. He hath broken my bones.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
He hath built up against me, And setteth round poverty and weariness.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
In dark places He hath caused me to dwell, As the dead of old.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
He hath hedged me about, and I go not out, He hath made heavy my fetter.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Also when I call and cry out, He hath shut out my prayer.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
He hath hedged my ways with hewn work, My paths He hath made crooked.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
A bear lying in wait He [is] to me, A lion in secret hiding-places.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
My ways He is turning aside, and He pulleth me in pieces, He hath made me a desolation.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
He hath trodden His bow, And setteth me up as a mark for an arrow.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
He hath caused to enter into my reins The sons of His quiver.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
I have been a derision to all my people, Their song all the day.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
He hath filled me with bitter things, He hath filled me [with] wormwood.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
And He breaketh with gravel my teeth, He hath covered me with ashes.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
And Thou castest off from peace my soul, I have forgotten prosperity.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
And I say, Perished hath my strength and my hope from Jehovah.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Remember my affliction and my mourning, Wormwood and gall!
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Remember well, and bow down doth my soul in me.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
This I turn to my heart — therefore I hope.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
The kindnesses of Jehovah! For we have not been consumed, For not ended have His mercies.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
New every morning, abundant [is] thy faithfulness.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
My portion [is] Jehovah, hath my soul said, Therefore I hope for Him.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Good [is] Jehovah to those waiting for Him, To the soul [that] seeketh Him.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Good! when one doth stay and stand still For the salvation of Jehovah.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Good for a man that he beareth a yoke in his youth.
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
He sitteth alone, and is silent, For He hath laid [it] upon him.
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
He putteth in the dust his mouth, if so be there is hope.
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
He giveth to his smiter the cheek, He is filled with reproach.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
For the Lord doth not cast off to the age.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
For though He afflicted, yet He hath pitied, According to the abundance of His kindness.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
For He hath not afflicted with His heart, Nor doth He grieve the sons of men.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
To bruise under one's feet any bound ones of earth,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
To turn aside the judgment of a man, Over-against the face of the Most High,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
To subvert a man in his cause, the Lord hath not approved.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Who [is] this — he hath said, and it is, [And] the Lord hath not commanded [it]?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
From the mouth of the Most High Go not forth the evils and the good.
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
What — sigh habitually doth a living man, A man for his sin?
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
We search our ways, and investigate, And turn back unto Jehovah.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
We lift up our heart on the hands unto God in the heavens.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
We — we have transgressed and rebelled, Thou — Thou hast not forgiven.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Thou hast covered Thyself with anger, And dost pursue us; Thou hast slain — Thou hast not pitied.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Thou hast covered Thyself with a cloud, So that prayer doth not pass through.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Offscouring and refuse Thou dost make us In the midst of the peoples.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Opened against us their mouth have all our enemies.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Fear and a snare hath been for us, Desolation and destruction.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Rivulets of water go down my eye, For the destruction of the daughter of my people.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mine eye is poured out, And doth not cease without intermission,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Till Jehovah looketh and seeth from the heavens,
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
My eye affecteth my soul, Because of all the daughters of my city.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Hunted me sore as a bird have my enemies without cause.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
They have cut off in a pit my life, And they cast a stone against me.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Flowed have waters over my head, I have said, I have been cut off.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
I called Thy name, O Jehovah, from the lower pit.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
My voice Thou hast heard, Hide not Thine ear at my breathing — at my cry.
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Thou hast drawn near in the day I call Thee, Thou hast said, Fear not.
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Thou hast pleaded, O Lord, the pleadings of my soul, Thou hast redeemed my life.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Thou hast seen, O Jehovah, my overthrow, Judge Thou my cause.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Thou hast seen all their vengeance, All their thoughts of me.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Thou hast heard their reproach, O Jehovah, All their thoughts against me,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
The lips of my withstanders, Even their meditation against me all the day.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Their sitting down, and their rising up, Behold attentively, I [am] their song.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Thou returnest to them the deed, O Jehovah, According to the work of their hands.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Thou givest to them a covered heart, Thy curse to them.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Thou pursuest in anger, and destroyest them, From under the heavens of Jehovah!