< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
I, am the man, that hath seen affliction, by the rod of his indignation;
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Me, hath he driven out and brought into darkness, and not light;
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Surely, against me, doth he again and again, turn his hand all the day.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
He hath worn out my flesh and my skin, hath broken my bones;
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
He hath built up against me, and carried round me, fortifications and a trench;
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
In dark places, hath he made me sit, like the dead of age-past times.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
He hath walled up around me, that I cannot get out, hath weighted my fetter;
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Yea, when I make outcry and implore, he hath shut out my prayer;
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
He hath walled in my ways with hewn stone, my paths, hath he caused to wind back.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
A bear lying in wait, he is to me, a lion, in secret places;
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
My ways, hath he turned aside, and hath torn me in pieces, hath made me desolate;
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
He hath trodden his bow, and set me up, as a mark for the arrow.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
He hath caused to enter my reins, the sons of his quiver;
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
I have become a derision to all my people, their song all the day;
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
He hath sated me with bitter things, hath drenched me with wormwood.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
And he hath crushed, with gravel-stones, my teeth, hath made me cower in ashes;
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
And thou hast thrust away from welfare, my soul, I have forgotten prosperity;
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
And I said, Vanished is mine endurance, even mine expectation, from Yahweh.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Remember my humiliation and my fleeings, the wormwood and poison;
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Thou wilt, indeed remember, that, bowed down concerning myself, is my soul;
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
This, will I bring back to my heart, therefore, will I hope.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
The lovingkindnesses of Yahweh, verily they are not exhausted, Verily! not at an end, are his compassions:
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
New things for the mornings! Abundant is thy faithfulness:
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
My portion, is Yahweh, saith my soul, For this cause, will I wait for him.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Good is Yahweh, to them who wait for him, to the soul that will seek him;
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
Good it is—both to wait and to be silent, for the deliverance of Yahweh;
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
Good it is for a man, that he should bear the yoke in his youth.
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
Let him sit alone, and keep silence, because he took it upon himself:
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
Let him put, in the dust, his mouth, peradventure, there is hope!
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Let him give, to him that smiteth him, his cheek, let him be sated with reproach.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Surely My Lord, will not cast off, unto times age-abiding;
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
Surely, though he cause grief, yet will he have compassion, according to the multitude of his lovingkindnesses;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
Surely he hath not afflicted from his heart, nor caused sorrow to the sons of men.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
To crush, under his feet, any of the prisoners of the earth;
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
To turn aside the right of a man, before the face of the Most High;
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
To oppress a son of earth in his cause, My Lord, hath made no provision.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Who was it that spake, and it was done, [when], My Lord, had not commanded?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Out of the mouth of the Most High, Proceed there not misfortunes and blessing?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Why should a living son of earth complain, [Let] a man [complain] because of his sins?
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Let us search out our ways, and examine them well, and let us return unto Yahweh;
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Let us lift up our heart, to the opened palms, to the Mighty One in the heavens;
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
We, have trespassed and rebelled, Thou, hast not pardoned.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Thou hast covered thyself with anger, and pursued us, hast slain—hast not spared;
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Thou hast screened thyself with the clouds, that prayer, should not pass through;
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Offscouring and refuse, dost thou make us, in the midst of the peoples.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
With their mouth, opened wide over us, [stand] all our foes.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Terror and a pit, have befallen us, tumult and grievous injury;
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
With streams of water, mine eye runneth down, over the grievous injury of the daughter of my people.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mine eye, poureth itself out and ceaseth not, without relief;
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Until Yahweh out of the heavens shall look forth, and see,
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Mine eye dealeth severely with my soul, because of all the daughters of my city.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
They, have laid snares, for me as a bird, who are mine enemies without cause:
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
They have cut off, in the dungeon, my life, and have cast a stone upon me;
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Waters, flowed over, my head, I said, I am cut off!
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
I have called upon thy Name, O Yahweh, out of the dungeon below;
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
My voice, thou hast heard, —do not close thine ear to my respite, to mine outcry;
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Thou drewest near, in the day I kept calling on thee, thou saidst, Do not fear!
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Thou hast pleaded, O My Lord, the pleas of my soul, hast redeemed my life;
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Thou hast beheld, O Yahweh, my failure to get justice, Pronounce thou my sentence;
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Thou hast seen all their vindictiveness, all their plots against me.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Thou hast heard their reproach, O Yahweh, all their plots against me;
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
The lips of mine assailants, and their mutterings, are against me, all the day;
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
On their downsitting and their uprising, do thou look, I, am their song.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Thou wilt render to them a recompense, O Yahweh, according to the work of their hands;
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Thou wilt suffer them a veiling of heart, thy curse to them;
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Thou wilt pursue in anger, and wilt destroy them, from under the heavens of Yahweh.

< Lamentations 3 >