< Lamentations 3 >
1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
I am the man that hath seen affliction under the rod of His wrath;
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
He hath led me and brought me into darkness, and not into light;
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Yea, against me doth he again and again turn his hand all the day long.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
My flesh and my skin hath he made old; he hath broken my bones.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
He hath builded against me, and encompassed me with bitterness and woe.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
He hath set me in dark places, as those that have long been dead.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
He hath hedged me about, so that I cannot get out; he hath made my chain heavy;
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Yea, when I cry and call aloud, he shutteth out my prayer.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
He blocketh up my way with hewn stone; he maketh my paths crooked.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
A bear lying in wait hath he been to me, a lion in lurking-places.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
He hath turned aside my ways, and torn me in pieces; he hath made me desolate.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
He hath bent his bow, and set me as a mark for the arrow.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
He hath caused the sons of his quiver to pierce my reins.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
I have been a laughing-stock to all my people, their song all the day.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
He hath filled me with bitterness; he hath made me drunk with wormwood.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
He hath also broken my teeth with gravel-stones; He hath covered me with ashes.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Yea, thou hast removed my soul far from peace; I have forgotten prosperity.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
And I say, “My confidence and my hope in Jehovah are gone!”
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Remember my affliction and my misery, the wormwood and the gall!
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Yea, thou wilt remember them, for my soul sinketh within me!
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
This I recall to my mind; therefore have I hope;
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
It is of the mercy of Jehovah that we are not consumed; yea, his compassion faileth not;
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
It is new every morning; great is thy faithfulness.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Jehovah is my portion, saith my soul, therefore do I hope in him.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Jehovah is good to them that trust in him, to the soul that seeketh him.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
It is good that a man hope, and quietly wait for salvation from Jehovah.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
It is good for a man that he bear the yoke in his youth;
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
That he sit alone and keep silence, since He layeth it upon him;
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
That he put his mouth in the dust, [[saying to himself, ]] “Perhaps there may be hope!”
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
That he offer his cheek to the smiter; that he be filled with reproach.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
For the Lord will not cast off forever;
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
For though he cause grief, yet doth he have compassion according to his great mercy;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
For he doth not willingly afflict and grieve the children of men.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Doth one trample under foot all the prisoners of the earth,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
Doth he bend the right of a man before the face of the Most High,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
Doth he subvert a man in his cause, and shall not the Lord behold it?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Who is he that saith, and it cometh to pass, when the Lord hath not commanded?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Cometh not evil, as well as good, from the mouth of the Most High?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Wherefore then murmureth the living man? Let him murmur at his own sin!
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Let us search and try our ways, and turn again to Jehovah!
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Let us lift up our hearts with our hands to God in the heavens!
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
We have transgressed; we have rebelled; thou hast not forgiven!
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Thou hast hidden thyself in anger, and hast pursued us; thou hast slain and hast not spared;
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Thou hast hidden thyself in a cloud, that our prayer may not pass through;
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Thou hast made us the offscouring and refuse in the midst of the nations.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
All our enemies have opened their mouths against us;
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Terror and the pit have come upon us, desolation and destruction;
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Mine eye runneth down with streams of water for the destruction of the daughter of my people.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mine eye trickleth down and ceaseth not, without any intermission,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Until Jehovah look down and behold from heaven.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Mine eye is painful to me on account of all the daughters of my city.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
They that are my enemies without cause hunt me down like a bird;
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
They take away my life in the dungeon; they cast a stone upon me;
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Waters flow over my head; I say, “I am undone!”
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
I call upon thy name, O Jehovah, from the deep dungeon;
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Hear thou my voice! hide not thine ear from my cry for relief!
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Be near to me, when I call upon thee! Say, “Fear not!”
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Thou maintainest my cause, O Lord; thou redeemest my life!
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Thou, O Jehovah, seest the wrong done to me; Maintain thou my cause!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Thou seest all their vengeance, all their devices against me.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Thou hearest their reproach, O Jehovah, all their devices against me,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
The words of my adversaries, and their machinations against me all the day long!
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Behold their sitting down and their rising up! I am their song.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Render to them a recompense, O Jehovah, according to the work of their hands!
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Give them blindness of mind! thy curse be upon them!
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Pursue them in thine anger, and destroy them from under Jehovah's heaven!