< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
I am the man who hath seen affliction by the rod of his wrath.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
Me hath he driven out, and led into darkness, but not into light.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Surely against me doth he turn again and again his hand all the day.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
He hath caused my flesh and my skin to wear out, he hath broken my bones.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
He hath built around me, and encompassed me with poison and hardship.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
In dark places hath he set me to dwell, like the dead of olden times.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
He hath placed a fence round about me, that I cannot get out; he hath made heavy my chain.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Also when I cry aloud and make entreaty, he shutteth out my prayer.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
He hath fenced up my ways with hewn stone, my paths hath he made crooked.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
A bear lying in wait is he to me, a lion in secret places.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
On my ways hath he placed thorns, and torn me in pieces: he hath made me desolate.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
He hath bent his bow, and placed me as a mark for the arrow.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
He hath caused to enter into my reins the children of his quiver.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
I am become a laughing-stock to all my people, their [jeering] song all the day.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
He hath sated me with bitter things, he hath made me drunken with wormwood.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
He hath also broken my teeth with gravel-stones, he hath covered me with ashes.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
And my soul hath given up all thoughts of peace: I forget happiness.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
And I said, Lost is my strength, my expectation also from the Lord.
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Remembering my affliction and [the cause of] my complaint, wormwood and poison.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Remembering [this] continually my soul is bowed down deeply within me.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
[Yet] this answer will I give to my heart: therefore will I wait [in confidence].
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
It is through the Lord's kindness that we are not consumed, because his mercies have no end;
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
They are new every morning: great is thy faithfulness.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
The Lord is my portion, saith my soul, therefore will I wait for him.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
The Lord is good unto those that hope in him, to the soul that seeketh him.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
It is good that one should wait and this in silence for the salvation of the Lord.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
It is good for a man that he bear the yoke in his youth;
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
That he sit in solitude and be silent; because He hath laid it upon him;
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
That he put his mouth in the dust; perhaps there still is hope;
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
That he offer his cheek to him that smiteth him; that he be satisfied with reproach.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
For the Lord will not cast off for ever;
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
But though he have caused grief, yet will he have mercy according to the abundance of his kindnesses.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
For he doth not afflict of his own will, and aggrieve the children of men.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
To crush under his feet all the prisoners of the earth,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
To pervert the justice [due to man] before the face of the Most High.
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
To subvert a man in his contest—should the Lord not see this?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Who is he that saith aught, and it cometh to pass, when the Lord hath not ordained it?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Do not out of the mouth of the Most High come both the evil things and the good?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Wherefore should a living man complain? let every man complain because of his sins.
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Let us search through and investigate our ways, and let us return to the Lord.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Let us lift up our heart with our hands unto God in the heavens.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
We have indeed transgressed and rebelled: thou hast truly not pardoned.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Thou hast covered [us] with thy anger, and made pursuit after us: thou hast slain, thou hast not pitied.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Thou hast covered thyself with a cloud, that no prayer should pass through.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
As something loathsome and rejected hast thou rendered us in the midst of the people.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
Wide have all our enemies opened against us their mouth.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Terror and a snare are come upon us, [with] desolation and breaches.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
With streams of water runneth my eye down, because of the breach of the daughter of my people.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
My eye trickleth down, and resteth not, without any intermission,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Till the Lord look down, and behold from heaven.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
My eye affecteth my soul because of all the daughters of my city.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Those who are my enemies, without a cause, have chased me about like a bird.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
They have shut up in the dungeon my life, and have cast stones upon me.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Waters streamed over my head: I said, I am cut off.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
I called on thy name, O Lord, out of the dungeon of the lowest depth.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Thou didst hear my voice: hide not thy ear to give me enlargement at my cry.
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Thou wast ever near on the day that I called on thee: thou saidst, Fear not.
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Thou didst plead, O Lord, the causes of my soul: thou didst [before this] redeem my life.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
Thou hast [now] seen, O Lord, the wrong I suffer: judge thou my cause.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Thou hast seen all their vengeance, all their plans against me.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Thou hast heard their reviling, O Lord, all their plans against me,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
The speeches of these that rise up against me, and their device against me all the day.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Oh look upon their sitting down, and their rising up: I am their [jeering] song.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Render unto them a recompense, O Lord, according to the work of their hands.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Give them confusion of heart, thy curse he upon them.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Pursue them in anger and destroy from under the heavens of the Lord.

< Lamentations 3 >