< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
I am the man, that hath seene affliction in the rod of his indignation.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
He hath ledde mee, and brought me into darkenes, but not to light.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Surely he is turned against me: he turneth his hand against me all the day.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
My flesh and my skinne hath he caused to waxe olde, and he hath broken my bones.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
He hath builded against me, and compassed me with gall, and labour.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
He hath set me in darke places, as they that be dead for euer.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
He hath hedged about mee, that I cannot get out: he hath made my chaines heauy.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Also when I cry and showte, hee shutteth out my prayer.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
He hath stopped vp my wayes with hewen stone, and turned away my paths.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
He was vnto me as a beare lying in waite, and as a Lion in secret places.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
He hath stopped my wayes, and pulled me in pieces: he hath made me desolate.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
He hath bent his bow and made me a marke for the arrow.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
Hee caused the arrowes of his quiuer to enter into my reines.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
I was a derision to all my people, and their song all the day.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
He hath filled me with bitternes, and made me drunken with wormewood.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
He hath also broken my teeth with stones, and hath couered me with ashes.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
Thus my soule was farre off from peace: I forgate prosperitie,
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
And I saide, My strength and mine hope is perished from the Lord,
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Remembring mine affliction, and my mourning, the wormewood and the gall.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
My soule hath them in remembrance, and is humbled in me.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
I consider this in mine heart: therefore haue I hope.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
It is the Lordes mercies that wee are not consumed, because his compassions faile not.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
They are renued euery morning: great is thy faithfulnesse.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
The Lord is my portion, sayth my soule: therefore wil I hope in him.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
The Lord is good vnto them, that trust in him, and to the soule that seeketh him.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
It is good both to trust, and to waite for the saluation of the Lord.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
It is good for a man that he beare the yoke in his youth.
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
He sitteth alone, and keepeth silence, because he hath borne it vpon him.
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
He putteth his mouth in the dust, if there may be hope.
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Hee giueth his cheeke to him that smiteth him: he is filled full with reproches.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
For the Lord will not forsake for euer.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
But though he sende affliction, yet will he haue compassion according to the multitude of his mercies.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
For he doeth not punish willingly, nor afflict the children of men,
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
In stamping vnder his feete all the prisoners of the earth,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
In ouerthrowing the right of a man before the face of the most high,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
In subuerting a man in his cause: the Lord seeth it not.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Who is he then that sayth, and it commeth to passe, and the Lord commandeth it not?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Out of the mouth of the most high proceedeth not euill and good?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Wherefore then is the liuing man sorowfull? man suffreth for his sinne.
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Let vs search and try our wayes, and turne againe to the Lord.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Let vs lift vp our hearts with our handes vnto God in the heauens.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
We haue sinned, and haue rebelled, therefore thou hast not spared.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
Thou hast couered vs with wrath, and persecuted vs: thou hast slaine and not spared.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
Thou hast couered thy selfe with a cloude, that our prayer should not passe through.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Thou hast made vs as the ofscouring and refuse in the middes of the people.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
All our enemies haue opened their mouth against vs.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Feare, and a snare is come vpon vs with desolation and destruction.
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Mine eye casteth out riuers of water, for the destruction of the daughter of my people.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Mine eye droppeth without stay and ceaseth not,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
Till the Lord looke downe, and beholde from heauen.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Mine eye breaketh mine heart because of all the daughters of my citie.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Mine enemies chased me sore like a birde, without cause.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
They haue shut vp my life in the dungeon, and cast a stone vpon me.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Waters flowed ouer mine head, then thought I, I am destroyed.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
I called vpon thy Name, O Lord, out of the lowe dungeon.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
Thou hast heard my voyce: stoppe not thine eare from my sigh and from my cry.
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Thou drewest neere in the day that I called vpon thee: thou saydest, Feare not.
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
O Lord, thou hast maintained the cause of my soule, and hast redeemed my life.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
O Lord, thou hast seene my wrong, iudge thou my cause.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Thou hast seene all their vengeance, and all their deuises against me.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
Thou hast heard their reproch, O Lord, and all their imaginations against me:
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
The lippes also of those that rose against me, and their whispering against me continually.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Behold, their sitting downe and their rising vp, how I am their song.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Giue them a recompence, O Lord, according to the worke of their handes.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
Giue them sorow of heart, euen thy curse to them.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
Persecute with wrath and destroy them from vnder the heauen, O Lord.

< Lamentations 3 >