< Lamentations 3 >
1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Jeg er den, der så nød ved hans vredes ris,
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
mig har han ført og ledt i det tykkeste Mulm,
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
ja, Hånden vender han mod mig Dagen lang.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Mit Bød og min Hud har han opslidt, brudt mine Ben,
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
han mured mig inde, omgav mig med Galde og Møje,
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
lod mig bo i Mørke som de, der for længst er døde.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Han har spærret mig inde og lagt mig i tunge Lænker.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Om jeg end råber og skriger, min Bøn er stængt ude.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
Han spærred mine Veje med Kvader, gjorde Stierne kroge.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
Han blev mig en lurende Bjørn, en Løve i Baghold;
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
han ledte mig vild, rev mig sønder og lagde mig øde;
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
han spændte sin Bue; lod mig være Skive for Pilen.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
Han sendte sit Koggers Sønner i Nyrerne på mig;
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
hvert Folk lo mig ud og smæded mig Dagen lang,
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
med bittert mætted han mig, gav mig Malurt at drikke.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
Mine Tænder lod han bide i Flint, han trådte mig i Støvet;
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
han skilte min Sjæl fra Freden, jeg glemte Lykken
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
og sagde: "Min Livskraft, mit Håb til HERREN er ude."
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
At mindes min Vånde og Flakken er Malurt og Galde;
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
min Sjæl, den mindes det grant den grubler betynget.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
Det lægger jeg mig på Sinde, derfor vil jeg håbe:
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
HERRENs Miskundhed er ikke til Ende, ikke brugt op,
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
hans Nåde er ny hver Morgen, hans Trofasthed stor.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
Min Del er HERREN, (siger min Sjæl, ) derfor håber jeg på ham.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
Dem, der bier på HERREN, er han god, den Sjæl, der ham søger;
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
det er godt at håbe i Stilhed på HERRENs Frelse,
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
godt for en Mand, at han bærer Åg i sin Ungdom.
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
Han sidde ensom og tavs, når han lægger det på ham;
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
han trykke sin Mund mod Støvet, måske er der Håb.
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Række Kind til den, der slår ham, mættes med Hån.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
Thi Herren bortstøder ikke for evigt,
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
har han voldt Kvide, så ynkes han, stor er hans Nåde;
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
ej af Hjertet plager og piner han Menneskens Børn.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
Når Landets Fanger til Hobe trædes under Fod,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
når Mandens Ret for den Højestes Åsyn bøjes,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
når en Mand lider Uret i sin Sag mon Herren ej ser det?
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Hvo taler vel, så det sker, om ej Herren byder?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Kommer ikke både ondt og godt fra den Højestes Mund?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Over hvad skal den levende sukke? Hver over sin Synd!
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Lad os ransage, granske vore Veje og vende os til HERREN,
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
løfte Hænder og Hjerte til Gud i Himlen;
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
vi syndede og stod imod, du tilgav ikke,
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
men hylled dig i Vrede, forfulgte os, dræbte uden Skånsel,
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
hylled dig i Skyer, så Bønnen ej nåed frem;
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
til Skarn og til Udskud har du gjort os midt iblandt Folkene.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
De opspærred Munden imod os, alle vore Fjender.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Vor Lod blev Gru og Grav og Sammenbruds Øde;
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Vandstrømme græder mit Øje, mit Folk brød sammen.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
Hvileløst strømmer mit Øje, det kender ej Ro,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
før HERREN skuer ned fra Himlen, før han ser til.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
Synet af Byens Døtre piner min Sjæl.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
Jeg joges som en Fugl af Fjender, hvis Had var grundløst,
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
de spærred mig inde i en Grube, de stenede mig;
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Vand strømmed over mit Hoved, jeg tænkte: "Fortabt!"
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
Dit Navn påkaldte jeg, HERRE, fra Grubens Dyb;
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
du hørte min Røst: "O, gør dig ej døv for mit Skrig!"
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
Nær var du den Dag jeg kaldte, du sagde: "Frygt ikke!"
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Du førte min Sag, o Herre, genløste mit Liv;
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
HERRE, du ser, jeg lider Uret. skaf mig min Ret!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
Al deres Hævnlyst ser du, alle deres Rænker,
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
du hører deres Smædeord HERRE, deres Rænker imod mig,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
mine Fjenders Tale og Tanker imod mig bestandig.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
Se dem, når de sidder eller står, deres Nidvise er jeg.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
Dem vil du gengælde, HERRE, deres Hænders Gerning,
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
gør deres Hjerte forhærdet din Forbandelse over dem!
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
forfølg dem i Vrede, udryd dem under din Himmel.