< Lamentations 2 >

1 Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀! Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀, láti ọ̀run sí ayé; kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
Jaj; de sűrű felhőt borított haragjában az Úr Sionnak leányára! az égből a földre veté Izráel ékességét, és nem emlékezett meg lábainak zsámolyáról az ő haragja napján.
2 Láìní àánú ni Olúwa gbé ibùgbé Jakọbu mì; nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀. Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
Elnyelte az Úr, nem kimélte Jákóbnak minden hajlékát, letörte haragjában Júda leányának erősségeit, a földre terítette; megfertőzteté az országot és fejedelmeit.
3 Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké gbogbo ìwo Israẹli. Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò nígbà tí àwọn ọ̀tá dé. Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
Felgerjedt haragjában letördelé Izráelnek minden szarvát; hátravoná jobbkezét az ellenség elől, Jákób ellen pedig mint lángoló tűz emésztett köröskörül.
4 Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra. Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
Feszítette kézívét, mint valami ellenség, kinyújtá jobbkezét, mint támadó, és megölt mindent, a mi a szemnek kivánatos; Sion leányának sátorában, mint a tüzet önté ki búsulását.
5 Olúwa dàbí ọ̀tá; ó gbé Israẹli mì. Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì ó pa ibi gíga rẹ̀ run. Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀ fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
Olyan volt az Úr, mint valami ellenség; elnyelte Izráelt, elnyelte minden palotáját, elrontá erősségeit, és megsokasította Júda leányának a búját, baját.
6 Ó mú ìparun bá ibi mímọ́, ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Sioni gbàgbé àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn; nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run ọba àti olórí àlùfáà.
És eltapodta sátorát, mint valami kertet, lerombolta gyülekezése helyét; elfeledtete az Úr a Sionon ünnepet és szombatot, és megútált haragja hevében királyt és papot.
7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀. Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́ àwọn odi ààfin rẹ̀; wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
Megvetette az Úr az ő oltárát, megútálta szent helyét; ellenség kezébe adá palotáinak kőfalait; zajt ütöttek az Úr házában, mint ünnepnapon.
8 Olúwa pinnu láti fa ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya. Ó gbé wọn sórí òsùwọ̀n, kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn. Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀ wọ́n ṣòfò papọ̀.
Gondolá az Úr, hogy lerontja Sion leányának kőfalát; kiterjeszté a mérőkötelet, nem vonta vissza kezét a pusztítástól, és siralomra jutott a bástya és a kőfal, együtt búslakodnak!
9 Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀; òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́. Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí òfin mọ́, àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
Kapui besülyedtek a földbe, elveszté és összetöré annak zárait; királya és fejedelmei a pogányok közt vannak. Nincsen törvény, sőt prófétái sem nyernek kijelentést az Úrtól.
10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́; wọ́n da eruku sí orí wọn wọ́n sì wọ aṣọ àkísà. Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
A földön ülnek, elnémultak Sion leányának vénei, port szórtak a fejökre; zsákba öltöztek, földre csüggesztették fejöket Jeruzsálemnek szűzei.
11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún, mo ń jẹ ìrora nínú mi, mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀ nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run, nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú ní òpópó ìlú.
Elsenyvedtek szemeim a könyhullatástól, belső részeim háborognak, májam a földre omlik az én népem leányának romlása miatt, mikor elalélt a kis gyermek és a csecsszopó a város utczáin.
12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn, “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe ní àwọn òpópónà ìlú, bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò láti ọwọ́ ìyá wọn.
Azt mondták anyjoknak: Hol a kenyér, meg a bor? mikor elaléltak, mint a sebesültek a város utczáin, mikor kilehelték lelköket anyjoknak kebelén.
13 Kí ni mo le sọ fún ọ? Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu? Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé, kí n lè tù ọ́ nínú, ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni? Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun. Ta ni yóò wò ọ́ sàn?
Mivel bizonyítsak melletted, mihez hasonlítsalak, Jeruzsálem leánya, mivel mérjelek össze téged, hogy megvígasztaljalak, Sionnak szűz leánya?! Bizony nagy a te romlásod, mint a tenger: kicsoda gyógyít meg téged?!
14 Ìran àwọn wòlíì rẹ jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n; wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ. Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.
A te prófétáid hazugságot és bolondságot hirdettek néked, és nem fedték fel a te álnokságodat, hogy elfordították volna fogságodat; hanem láttak tenéked hazug és megtévelyítő prófétálásokat.
15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí; wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu: “Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní àṣepé ẹwà, ìdùnnú gbogbo ayé?”
Összecsapják feletted kezöket minden járó-kelők; süvöltenek és csóválják fejöket Jeruzsálem leánya felett: Ez-é az a város, a melyről azt mondták: tökéletes szépség, az egész földnek öröme?
16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn gbòòrò sí ọ; wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán. Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí; tí a sì wá láti rí.”
Feltátották ellened szájokat minden ellenségeid; süvöltenek és csikorgatják fogukat, mondván: Nyeljük el őt! Bizony ez a nap az, a melyet vártunk; megértük, látjuk!
17 Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu; ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ, tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́. Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú, ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ, ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.
Megcselekedte az Úr, a miket gondolt; beváltotta szavát, a melyet szólt eleitől fogva; rombolt és nem kimélt, és megvidámította rajtad az ellenséget, felemelte szarvát a te szorongatóidnak.
18 Ọkàn àwọn ènìyàn kígbe jáde sí Olúwa. Odi ọmọbìnrin Sioni, jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò ní ọ̀sán àti òru; má ṣe fi ara rẹ fún ìtura, ojú rẹ fún ìsinmi.
Kiáltott az ő szívök az Úrhoz: Oh Sion leányának kőfala! Folyjon alá könnyed mint a patak, éjjel és nappal; ne szakadjon félbe, síró szemed meg se pihenjen.
19 Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́, bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀ tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi níwájú Olúwa. Gbé ọwọ́ yín sókè sí i nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀ tí ó ń kú lọ nítorí ebi ní gbogbo oríta òpópó.
Kelj fel, riadj éjjel, az őrjárások kezdetén; öntsd ki, mint a vizet a te szívedet az Úr szine előtt; emeld fel hozzá kezeidet a te kisdedeidnek életéért, a kik elaléltak az éhség miatt minden utczának szegletén.
20 “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó. Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí. Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún? Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì ní ibi mímọ́ Olúwa?
Lásd meg Uram és tekintsd meg, kivel cselekedtél így! Avagy megegyék-é az asszonyok az ő méhöknek gyümölcsét, dédelgetett kisdedeiket; avagy megölettessék-é az Úrnak szent helyén pap és próféta?
21 “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀ sínú eruku àwọn òpópó; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ti ṣègbé nípa idà. Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ, Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.
Az utczákon a földön fekszik gyermek és vén; szűzeim és ifjaim fegyver miatt hullottak el; öldököltél haragod napján, mészároltál, nem kiméltél.
22 “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè, bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi. Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè; àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn, ni ọ̀tá mi parun.”
Egybehívtad mint valami ünnepnapra az én rettegtetőimet mindenfelől, és nem volt az Úr haragjának napján, a ki elmenekült és megszabadult volna. A kiket dédelgettem és felneveltem, ellenségem emésztette meg őket!

< Lamentations 2 >