< Lamentations 2 >

1 Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀! Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀, láti ọ̀run sí ayé; kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
Hĩ! Kaĩ Mwathani nĩakĩhumbĩrĩte Mwarĩ wa Zayuni na itu rĩa marakara make-ĩ! Nĩatungumanĩtie riiri wa Isiraeli, akaũharũrũkia kuuma igũrũ nginya thĩ; ndaaririkanire gaturwa ka magũrũ make, mũthenya ũrĩa aarakarire.
2 Láìní àánú ni Olúwa gbé ibùgbé Jakọbu mì; nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀. Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
Mwathani-rĩ, nĩameretie itũũro ciothe cia Jakubu atarĩ na tha; nĩamomorete ciĩhitho iria nũmu cia Mwarĩ wa Juda arĩ na marakara. Nĩagũithĩtie ũthamaki wa Mwarĩ wa Juda, na akagũithia anene ake, akamaconorithia.
3 Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké gbogbo ìwo Israẹli. Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò nígbà tí àwọn ọ̀tá dé. Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
Rũhĩa rwa Isiraeli ruothe arũrengete arĩ na marakara mahiũ. Nĩeheretie guoko gwake kwa ũrĩo, gũkameeherera o rĩrĩa thũ ciamakuhĩrĩria. Nĩgũcina acinĩte Jakubu ta mwaki ũkũrĩrĩmbũka, ũrĩa ũcinaga kĩrĩa gĩothe kĩrĩ hakuhĩ naguo.
4 Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra. Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
Ageetete ũta wake o ta thũ; guoko gwake kwa ũrĩo nĩ kwĩhaarĩirie. Arĩa othe maatũire makenagia maitho-rĩ, amooragĩte o ta marĩ thũ; hema ya Mwarĩ wa Zayuni amĩitĩrĩirie mangʼũrĩ make mahaana ta mwaki.
5 Olúwa dàbí ọ̀tá; ó gbé Israẹli mì. Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì ó pa ibi gíga rẹ̀ run. Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀ fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
Mwathani-rĩ, atuĩkĩte ta thũ; nĩameretie Isiraeli. Nĩameretie nyũmba ciake ciothe cia ũthamaki, na akaananga ciĩhitho ciake iria nũmu. Nĩaingĩhĩirie Mwarĩ wa Juda gũcakaya na kũgirĩka.
6 Ó mú ìparun bá ibi mímọ́, ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Sioni gbàgbé àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn; nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run ọba àti olórí àlùfáà.
Nĩonũhĩte gĩikaro gĩake ta mũgũnda; nĩanangĩte handũ hake ha gũtũnganĩrwo. Jehova nĩatũmĩte Zayuni ariganĩrwo nĩ ciathĩ ciake iria njathane, o hamwe na Thabatũ ciake; nĩ ũndũ wa marakara make mahiũ-rĩ, akanyarara mũthamaki, o hamwe na mũthĩnjĩri-Ngai.
7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀. Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́ àwọn odi ààfin rẹ̀; wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
Mwathani nĩaregete kĩgongona gĩake, na agatiganĩria handũ hake harĩa haamũre. Nĩaneanĩte thingo cia nyũmba ciake cia ũthamaki kũrĩ thũ; iraanĩrĩra irĩ thĩinĩ wa nyũmba ya Jehova, o taarĩ mũthenya wa gĩathĩ kĩrĩa gĩathane.
8 Olúwa pinnu láti fa ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya. Ó gbé wọn sórí òsùwọ̀n, kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn. Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀ wọ́n ṣòfò papọ̀.
Jehova nĩatuire itua rĩa kũmomora rũthingo rũrĩa rũthiũrũrũkĩirie Mwarĩ wa Zayuni. Nĩatambũrũkirie rũrigi rwa gũthima, na ndaagiririe guoko gwake gũtige kũrwananga. Nĩatũmire njirigo na thingo icakaye; o cierĩ igĩgĩtuĩka cia kwanangĩka.
9 Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀; òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́. Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí òfin mọ́, àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
Ihingo ciakuo nĩihorokeire na thĩ; mĩgĩĩko yacio nĩamiunangĩte, akamĩananga. Mũthamaki na anene akuo nĩmatahĩtwo magatwarwo ndũrĩrĩ-inĩ, watho rĩu ndũrutanagwo, na anabii akuo nĩmatigire kuona cioneki ciumĩte kũrĩ Jehova.
10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́; wọ́n da eruku sí orí wọn wọ́n sì wọ aṣọ àkísà. Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
Athuuri a kũu kwa Mwarĩ wa Zayuni maikarĩte thĩ makirĩte ki; nao nĩmehurĩirie rũkũngũ mĩtwe, na makehumba nguo cia makũnia. Airĩtu a Jerusalemu mainamĩrĩire maturumithĩtie mĩtwe yao thĩ.
11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún, mo ń jẹ ìrora nínú mi, mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀ nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run, nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú ní òpópó ìlú.
Maitho makwa nĩmaroora nĩ kũrĩra, ngatangĩka thĩinĩ wakwa, naguo roho wakwa nĩũitũrũrĩirwo thĩ nĩ ũndũ wa andũ akwa kwanangwo, nĩgũkorwo twana na tũkenge tũraringĩkĩra njĩra-inĩ cia itũũra rĩrĩa inene.
12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn, “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe ní àwọn òpópónà ìlú, bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò láti ọwọ́ ìyá wọn.
Tũrooria manyina atĩrĩ, “Irio na ndibei irĩ ha?” o tũkĩringĩkaga ta andũ matiihĩirio njĩra-inĩ cia itũũra rĩrĩa inene, o mĩoyo yatuo ĩgĩthiragĩra moko-inĩ ma manyina.
13 Kí ni mo le sọ fún ọ? Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu? Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé, kí n lè tù ọ́ nínú, ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni? Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun. Ta ni yóò wò ọ́ sàn?
Ingĩkiuga atĩa nĩ ũndũ waku? Ingĩkũgerekania nakĩ, wee Mwarĩ ũyũ wa Jerusalemu? Ingĩkũhaanania nakĩ, nĩguo ngũhoorerie, wee Mwarĩ ũyũ Gathirange wa Zayuni? Kĩronda gĩaku kĩrikĩte o ta iria. Nũũ ũngĩhota gũkũhonia?
14 Ìran àwọn wòlíì rẹ jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n; wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ. Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.
Cioneki iria anabii aku moonaga ciarĩ cia tũhũ na cia maheeni; matiigana kũmũguũrĩria mehia manyu nĩguo magirĩrĩrie gũtahwo kwanyu. Ndũmĩrĩri iria maamũheire ciarĩ cia maheeni, na cia kũmũhĩtithia.
15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí; wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu: “Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní àṣepé ẹwà, ìdùnnú gbogbo ayé?”
Ehĩtũkĩri othe mahũũraga hĩ; mathekaga makĩinainagĩria Mwarĩ ũyũ wa Jerusalemu mĩtwe, makĩũragia atĩrĩ: “Ĩĩ rĩĩrĩ nĩrĩo itũũra inene rĩrĩa rĩetagwo ũthaka ũrĩa mũkinyanĩru biũ, na rĩgeetwo gĩkeno gĩa thĩ yothe?”
16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn gbòòrò sí ọ; wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán. Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí; tí a sì wá láti rí.”
Thũ ciaku ciothe ciathamagia tũnua igũũkĩrĩre; igũthekagĩrĩra na ikahagarania magego, ikoiga atĩrĩ, “Ithuĩ nĩtũmũmeretie. Ũyũ nĩguo mũthenya ũrĩa tũtũire twetereire, na rĩu nĩtũwonete.”
17 Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu; ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ, tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́. Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú, ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ, ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.
Jehova nĩarĩkĩtie gwĩka ũrĩa aathugundĩte; we nĩahingĩtie kiugo gĩake, kĩrĩa aathanire o matukũ ma tene. Akũngʼaũranĩtie ategũkũiguĩra tha, atũmĩte thũ igũkenerere, rũhĩa rwa amuku aku nĩruo atũgĩrĩtie.
18 Ọkàn àwọn ènìyàn kígbe jáde sí Olúwa. Odi ọmọbìnrin Sioni, jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò ní ọ̀sán àti òru; má ṣe fi ara rẹ fún ìtura, ojú rẹ fún ìsinmi.
Ngoro cia andũ nĩirakaĩra Mwathani. Atĩrĩrĩ, wee rũthingo rũrũ rwa Mwarĩ wa Zayuni, reke maithori maku manyũrũrũke ta rũũĩ mũthenya na ũtukũ; ndũkahurũke, kana ũreke maitho maku mahurũke.
19 Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́, bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀ tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi níwájú Olúwa. Gbé ọwọ́ yín sókè sí i nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀ tí ó ń kú lọ nítorí ebi ní gbogbo oríta òpópó.
Arahũka, ũkayũrũrũke ũtukũ, rĩrĩa ũrangĩri wa ũtukũ wambagĩrĩria; itũrũraga ngoro yaku ta maaĩ mbere ya Mwathani. Ambararia moko maku na igũrũ kũrĩ we nĩ ũndũ wa mĩoyo ya ciana ciaku, o icio iraringĩka nĩ ngʼaragu magomano-inĩ ma njĩra ciothe.
20 “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó. Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí. Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún? Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì ní ibi mímọ́ Olúwa?
“Wee Jehova, ta rora, na ũcũũranie: Nũũ ũngĩ wee ũrĩ weka ũguo? Andũ-a-nja nĩmagĩrĩirwo nĩ kũrĩa maciaro mao, o ciana iria marerete? Mũthĩnjĩri-Ngai na mũnabii nĩmagĩrĩire kũũragagĩrwo handũ-harĩa-haamũre ha Mwathani?
21 “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀ sínú eruku àwọn òpópó; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ti ṣègbé nípa idà. Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ, Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.
“Andũ ethĩ o na arĩa akũrũ makomete hamwe rũkũngũ-inĩ rwa njĩra, aanake akwa na airĩtu moragĩtwo na rũhiũ rwa njora. Ũmoragĩte mũthenya ũrĩa ũrakarĩte; ũmoragĩte ũtekũmaiguĩra tha.
22 “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè, bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi. Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè; àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn, ni ọ̀tá mi parun.”
“O ta ũrĩa wĩtanaga mũthenya wa gĩathĩ-rĩ, noguo ũnjĩtĩire maũndũ ma kũnguoyohia, makandigiicĩria mĩena yothe o taarĩ mũthenya wa gĩathĩ. Mũthenya wa marakara ma Jehova-rĩ, gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wahonokire kana agĩtigara; arĩa ndarũmbũirie na ngĩrera-rĩ, thũ yakwa nĩĩmanangĩte.”

< Lamentations 2 >